1. Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san,Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
2. Gbé ara Rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé;san ẹ̀san fún agbéragaohun tí ó yẹ wọ́n.
3. Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwatí àwọn ẹni búburúyóò kọ orin ayọ̀?
4. Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbérága jáde;gbogbo àwọn olùṣebúburúkún fún ìṣògo.
5. Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn Rẹ túútúú, Olúwa:wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní Rẹ̀ lójú.
6. Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò,wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba,
7. Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i;Ọlọ́run Jákọ́bù kò sì kíyèsí i.”
8. Kíyèsí i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyànẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
9. Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bi?Ẹni tí ó dá ojú?Ó ha lè ṣe láìríran bi?
10. Ẹni tí ń bá orílẹ̀ èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni sọ́nà bí?Ẹni ti ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
11. Olúwa mọ èrò inú ènìyàn;ó mọ̀ pé aṣán ni wọ́n.
12. Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tíìwọ báwí, Olúwa,ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin Rẹ;
13. Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi,títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
14. Nítorí Olúwa kò ní kọ̀ àwọn ènìyàn Rẹ̀ sílẹ̀;Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní Rẹ̀ sílẹ̀.
15. Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo,àti gbogbo àwọn ọlọ́kàndídúró ṣinṣin yóò tẹ̀ lé e lẹ́yìn.
16. Ta ni yóò dìde fún misí àwọn olùṣe búburú?Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
17. Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́,èmi fẹ́rẹ̀ má a gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́
18. Nígbà tí mo sọ pé “ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ Rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
19. Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi,ìtùnú Rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
20. Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú Rẹẹni tí ń fí òfin dìmọ̀ ìwà ìkà?
21. Wọ́n kó ara wọn jọ si olódodowọ́n sì ń dá àwọn aláìsẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
22. Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi,àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹnití mo ti ń gba ààbò.
23. Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọnyóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.