1. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fúnMá ṣe dákẹ́
2. Nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tànti ya ẹnu wọn sí miwọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi
3. Wọn fi ọ̀rọ̀ ìrira yí mi káàkiri;wọ́n bá mi ja láìnídìí
4. Nípo ifẹ̀ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi,ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
5. Wọ́n sì fi ibi san ire fún miàti ìríra fún ìfẹ́ mi.
6. Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojú kọ ọ́jẹ́ kí àwọn olufisùndúró ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ̀.
7. Kí a dá a lẹbi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́kí àdúrà Rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀
8. Kí ọjọ́ Rẹ̀ kí ó kúrúkí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ Rẹ̀
9. Kí àwọn ọmọ Rẹ̀ di aláìní babakí aya Rẹ̀ sì di opó
10. Jẹ́ kí àwọn ọmọ Rẹ̀ máa ṣagbe kirikí wọn máa tọrọ ounjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn
11. Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó níjẹ́ kí àléjò kí o kó èrè isẹ́ Rẹ̀ lọ
12. Má ṣe jẹ́ kí ẹnikan ṣe àánú fún untàbí kí wọn káàánú lóríàwọn ọmọ Rẹ̀ aláìní baba
13. Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ Rẹ̀ kúròkí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀
14. Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba Rẹ̀ kíó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ OlúwaMá ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò
15. Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwakí o le ge ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
16. Nítorí kò rántí láti ṣàánú,ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíní sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú,kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
17. Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí Rẹ̀:bi inú Rẹ̀ kò ti dùn si ire, bẹ́ẹ̀ ni ki ó jìnnà sí ì.
18. Bí ó ti fi ègún wọ ará Rẹ̀ lásọ bí ẹ̀wùbẹ́ẹ̀ ni kí ó wá si inú Rẹ̀ bí omi
19. Jẹ́ kí o rí fún un bí aṣọ tí a dàbòó níara, àti fún àmùrè ti ó fi gbàjá nígbà gbogbo
20. Èyí ni èrè àwọn ọ̀ta mi làti ọwọ́ Olúwa wá;àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọ̀kàn mi.
21. Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa,ṣe rere fún mi nítorí orúkọ RẹNítorí ti àánú Rẹ dara, ìwọ gbà mí
22. Nítorí pé talákà àti aláìní ni mí,àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
23. Èmi ń kọja lọ bí òjiji tí óńfà sẹ́yìn,mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
24. Eékún mi di aláìlera nítorí ààwẹ̀ gbígbàẹran ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
25. Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi;nígbà tí wọn wò mí, wọn gbọn orí wọn.
26. Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi;gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ Rẹ.
27. Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ Rẹ ni èyíwí pé ìwọ, Olúwa, ni o ṣe é.
28. Wọ́n o máa gégùn-ún, ṣùgbọ́n ìwọ má súré;Nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n,ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ Rẹ yóò yọ̀
29. Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjúkí á sì fi ìdàrú dàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
30. Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yìn Olúwa gidigidiní àárin ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín
31. Nítorí ó dúró ni apá ọ̀tún aláìníláti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn Rẹ̀ lẹ́bi.