orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42
  43. 43
  44. 44
  45. 45
  46. 46
  47. 47
  48. 48
  49. 49
  50. 50
  51. 51
  52. 52
  53. 53
  54. 54
  55. 55
  56. 56
  57. 57
  58. 58
  59. 59
  60. 60
  61. 61
  62. 62
  63. 63
  64. 64
  65. 65
  66. 66

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ègbé Ni Fún Ìlúu Dáfídì

1. Ègbé ni fún ọ, Áríẹ́lì, Áríẹ́lì,ìlú níbi tí Dáfídì tẹ̀dó sí!Fi ọdún kún ọdúnsì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀ṣíwájú.

2. Ṣíbẹ̀ ṣíbẹ̀ èmi yóò dó ti Áríẹ́lìòun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sunkún,òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.

3. Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo;Èmi yóò sì fi ilé-ìṣọ́ yí ọ ká:èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdótini mi dojú kọ ọ́.

4. Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá;ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀.Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti iwin láti ilẹ̀ wá,láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹyóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.

5. Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná,agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù.Lójijì, ní ìṣẹ́jú àáyá,

6. Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wápẹ̀lú àrá, ilẹ̀ ríri àti ariwo ńláàti ẹ̀fúúfù líle àti iná ajónirunorílẹ̀ èdè tí ó bá Áríẹ́lì jà,tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódì rẹ̀tí ó sì dó tì í,yóò dàbí ẹni pé nínú àlá,bí ìran ní òru

7. Lẹ́yìn náà,ọ̀gọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo

8. àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá péòun ń jẹun,ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lúu rẹ̀;àti bí ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ lá àlá péòun ń mumi,ṣùgbọ́n nígbà tí ó yajú pẹ́ ẹ́, pẹ̀lú òùngbẹtí kò dáwọ́ dúró ni.Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdètí ń bá òkè Ṣíhónì jà.

9. Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín,ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran;ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì,ẹ ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n, ṣùgbọ́n kì í se ti ọtí bíà.

10. Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sóríi yín:ó ti dì yín lójú (ẹ̀yin wòlíì);ó ti bo oríi yín (ẹ̀yin aríran).

11. Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”

12. Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”

13. Olúwa wí pé:“Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọnwọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn,ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi.Ìsìn wọn fún mini a gbé ka orí òfin tí àwọnọkùnrin kọ́ ni.

14. Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yaàwọn ènìyàn yìí lẹ́nupẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu;ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé,ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”

15. Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbunláti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa,tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùntí wọ́n sì rò pé,“Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”

16. Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀,bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀!Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé“Òun kọ́ ló ṣe mí”?Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé,“kò mọ nǹkan”?

17. Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́a kò ní sọ Lẹ́bánónì di pápá ẹlẹ́tù lójúàti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí ihà?

18. Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà,láti inú fìrífìrí àti òkùnkùnni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.

19. Lẹ́ẹ̀kan síi àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa:àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Ísírẹ́lì.

20. Aláìláàánú yóò pòórá,àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò dàwátì,gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—

21. àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi,ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní kóòtùtí ẹ fi ẹ̀rí èkè dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.

22. Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Ábúráhámù padà sọ sí ilé Jákọ́bù:“Ojú kì yóò ti Jákọ́bù mọ́;ojúu wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.

23. Nígbà tí wọ́n bá ríi láàrin àwọn ọmọ wọn,àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi,wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́,wọn yóò tẹ́wọ́gba mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jákọ́bùwọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

24. Gbogbo àwọn tí ń rìn ṣégeṣège ní ẹ̀mí yóò jèrè ìmọ̀;gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”