orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42
  43. 43
  44. 44
  45. 45
  46. 46
  47. 47
  48. 48
  49. 49
  50. 50
  51. 51
  52. 52
  53. 53
  54. 54
  55. 55
  56. 56
  57. 57
  58. 58
  59. 59
  60. 60
  61. 61
  62. 62
  63. 63
  64. 64
  65. 65
  66. 66

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Àsọtẹ́lẹ̀ Nípa Jérúsálẹ́mù

1. Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ àfonífojì ti ìran:Kí ni ó ń dààmú un yín báyìí,tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ,

2. Ìwọ ìlú tí ó kún fún dàrúdàpọ̀,Ìwọ ìlú rúkèrúdò òun rògbòdìyànÀwọn tó ṣubú nínú un yín ni a kò fi idà pa,tàbí ojú ogun ni wọ́n kú sí.

3. Gbogbo àwọn olóríi yín ti jùmọ̀ sálọ;a ti kó wọn nígbékùn láì lo ọrun ọfà.Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀,lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀ta sì wàlọ́nà jínjìnréré.

4. Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi:jẹ́ kí n ṣunkún kíkorò.Má ṣe gbìyànjú àti tùmí nínúnítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”

5. Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kantí rúkèrúdò, rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ní àfonífojì ìmọ̀,ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀àti síṣun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.

6. Élámù mú àpò-ọfà lọ́wọ́,pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin,kírí yọ apata rẹ̀ síta.

7. Àyànfẹ́ àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́-ogun,àwọn ẹlẹ́ṣin ni a sọdó sí ẹnu bodè ìlú;

8. gbogbo ààbò Júdà ni a ti ká kúrò.Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náàsí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú ihà,

9. Ìwọ rí i pé ìlúu Dáfídìní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ààyè níbi ààbò rẹ̀,ìwọ ti tọ́jú omisínú adágún ti ìsàlẹ̀.

10. Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jérúsálẹ́mùó sì wó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé lulẹ̀ láti fún ìgànná lágbára.

11. Ìwọ mọ agbemi sí àárin ògiri méjìfún omi inú adágún àtijọ́,ṣùgbọ́n ìwọ kò wo ẹni tí ó ṣe é tẹ́lẹ̀tàbí kí o kọbi ara sí ẹni tí ógbérò rẹ̀ ní ìgbà pípẹ́ ṣẹ́yìn.

12. Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun,pè ọ́ ní ọjọ́ náàláti ṣunkún kí o sì pohùnréré,kí o tu irun rẹ dànù kí o sìda aṣọ ọ̀fọ̀ bora.

13. Ṣùgbọ́n Wòó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wàmàlúù pípa àti àgùntàn pípa,ẹran jíjẹ àti ọtí wáìnì mímu!“Jẹ́ kí a jẹ kí a mu,” ni ẹ̀yin wí,“Nítorí pé lọ́la àwa ó kú!”

14. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mímọ̀ létíì mi: “Títí di ọjọ́ ikúu yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

15. Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:Lọ, sọ fún ìríjú yìí pé,fún Ṣébínà, ẹni tí ààfin wà ní ìkáwọ́ọ rẹ̀:

16. Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín-yìí àti péta ni ó sì fún ọ ní àṣẹláti gbẹ́ ibojì kan fún ara rẹ níhìn-ín-yìí,tí ó gbẹ́ ibojì ní ibi gígatí ó sì gbẹ́ ibi ìsinmi rẹ nínú àpáta?

17. “Kíyèṣára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígíríkí ó sì jù ọ́ nù, Ìwọ ọkùnrin alágbára.

18. Òun yóò ká ọ rúgúdú bí i bọ́ọ̀lùyóò sì sọ ọ́ sí orílẹ̀ èdè ńlá kan.Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú síàti níbẹ̀ pẹ̀lú ni àwọn kẹ̀kẹ́ ogunàràmọ̀ǹdà rẹ yóò wà—ìwọ ìtìjú sí ilé ọ̀gá rẹ!

19. Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ,a ó sì lé ọ kúrò ní ipò rẹ.

20. “Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliákímù ọmọ Hílíkíyà.

21. Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́ n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jérúsálẹ́mù àti fún ilée Júdà.

22. Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilée Dáfídì lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá sí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ẹnikẹ́ni kì yóò le è sí.

23. Èmi yóò sì kàn án mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní àyèe rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀.

24. Gbogbo ògo ìdílée rẹ̀ ni yóò rọ̀ mọ́ ọn ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ gbogbo ohun èlò aláìlágbára láti orí abọ́ rẹ̀ dé orí ìdẹ̀ rẹ̀.

25. “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní àyèe rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lóríi rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.