orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Heṣekíàyà Ọba Júdà

1. Ní ọdún kẹta Hóséà ọmọ Élà ọba Ísírẹ́lì, Heṣekíàyà ọmọ Áhásì ọba Júdà bẹ̀rẹ̀ ìjọba.

2. Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ A bì ọmọbìnrin Ṣakaríàyà.

3. Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dáfídì ti ṣe.

4. Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ òkúta àwọn ère ó sì gé àwọn ère lulẹ̀ ó sì fọ́ ejò idẹ náà túútúú tí Móṣè ti ṣe, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Néhúṣítanì.)

5. Heṣekáyà sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì. Kò sì sí ẹnìkan tí ó dàbí tirẹ̀ lára gbogbo àwọn ọba Júdà, bóyá kí ó tó jẹ tàbí lẹ́yìn rẹ̀.

6. Ó sún mọ́ Olúwa, kò sì dẹ́kun láti tì í lẹ́yìn: ó sì pa òfin Olúwa mọ́ tí ó ti fi fún Mósè.

7. Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀; ó sì ń ṣe rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé. Ó ṣe ọ̀tẹ̀ sí ọba Ásíríà kò sì sìn-ín.

8. Láti ilé-ìṣọ́ títí dé ìlú olódi, ó sì pa àwọn ará Fílístínì run, àti títí dé Gásà àti agbègbè rẹ̀.

9. Ní ọdún kẹrin ọba Heṣekáyà, nígbà tí ó jẹ́ ọdún keje Hóséà ọmọ Élà ọba Ísírẹ́lì. Ṣálímánésérì ọba Áṣíríà yàn lára Ṣamáríà ó sì tẹ̀dó tì í.

10. Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Ásíríà gbé e. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó Ṣamáríà ní ọdún kẹfà Heṣekáyà tí ó sì jẹ́ ọdún kẹsàn-án Hóṣéà ọba Ísírẹ́lì.

11. Ọba Áṣíríà lé Ísírẹ́lì kúrò ní Áṣíríà, wọ́n sì ṣe àtìpó wọn ní Hálà, ní Gósánì létí odò Hábórì àti ní ìlú àwọn ará Médíà.

12. Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wọn kò pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Ṣùgbọ́n wọ́n ti dà májẹ̀mú rẹ̀ gbogbo èyí tí Móṣè ìránṣẹ́ Olúwa ti pa láṣẹ. Wọn kò fi etí wọn sílẹ̀ sí òfin wọn kò sì gbé wọn jáde.

13. Ní ọdún kẹrìnlá tí Heṣekáyà jọba, Ṣenakérúbù ọba Ásíríà kọlu gbogbo ìlú olódi ti Júdà ó sì pa wọ́n run.

14. Bẹ́ẹ̀ ni Heṣekáyà ọba Júdà rán oníṣẹ́ yìí sí ọba Áṣíríà ní Lákísì, “Mo ti mú ìṣe ohun tí kò dára kúrò lọ́dọ̀ mi, èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba bu ọ̀ọ́dúnrún talẹ́ntì fàdákà àti ọgbọ̀n talẹ́ntì wúrà.

15. Heṣekáyà fún un ní gbogbo fàdákà tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa àti nínú ilé ìṣúra ọba.

16. Ní àkókò yìí Heṣekáyà ọba Júdà ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Heṣekáyà ọba Júdà ti gbéró ó sì fi fún ọba Ásíríà.

Ṣenakérúbù Halẹ̀ Mọ́ Jérúsálẹ́mù

17. Ọba Ásíríà rán alákòóṣo gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ ogun tí ó pọ̀, láti Lákísì sí ọba Heṣekáyà ní Jérúsálẹ́mù. Wọ́n wá sí òkè Jérúsálẹ́mù wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá Alágbàfọ̀.

18. Wọ́n sì pe ọba; àti Eliákímù ọmọ Hílíkíyà ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣébínà akọ̀wé, àti Jóà ọmọkùnrin Ásáfù tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.

19. Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Heṣekáyà pé:“ ‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Ásíríà sọ: Lórí kí ni ìwọ ń dá ìgbóyà rẹ̀ yìí?

20. Ìwọ wí pé ìwọ ni ẹ̀tà àti ti ogun alágbára ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo nìkan, lórí ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?

21. Wò ó Nísinsìn yìí ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Éjíbítì, ẹ̀rún igi pẹlẹbẹ ọ̀pá ìyè lórí ọ̀pá, èyí tí yóò wọ inú ọwọ́ ọkùnrin tí ó sì pa á lára tí ó bá fi ara tìí Irú rẹ̀ ni Fáráò ọba Éjíbítì fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.

22. Tí ìwọ bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀ wa lé Olúwa Ọlọ́run.” Òun ha kọ́ ní ẹnìkan náà tí ibi gíga àti àwọn pẹpẹ tí Heṣekáyà mú kúrò, tí ó wí fún Júdà àti Jérúsálẹ́mù pé, “O gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí ní Jérúsálẹ́mù”?

23. “ ‘Wá Nísinsìn yìí, ṣe àdéhùn pẹ̀lú ọ̀gá mi, ọba Áṣíríà: Èmi yóò sì fún ọ ní ẹgbàá ẹṣin (2000) tí ìwọ bá lè kó àwọn tí yóò gùn ún sí orí rẹ!

24. Báwo ni ìwọ yóò ṣe le padà sẹ́yìn ọ̀kan lára àwọn oníṣẹ́, tí ó gbẹ̀yìn lára àwọn oníṣẹ́ ọ̀gá mi, tí ó bá tilẹ̀ jẹ́ pé; ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀ yín lé Éjíbítì fún àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin?

25. Síwájú síi, èmi ti wá láti mú àti láti parun ibíyìí láìsí ọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ sọ fún mi pé kí n yára láti yan lórí ìlú yìí, kí n sì paárun.’ ”

26. Nígbà náà Éláékímù ọmọ Hílíkíáyà, àti ṣébínà àti Jóà sọ fún olùdarí pápá pé, “Jọ̀wọ́ sọ̀rọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ ní èdè Ṣíríà, nítorí ti ó tí yé wa, má ṣe sọ̀rọ̀ fún wa pẹ̀lú èdè Hébérù ní etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn tí ń bẹ lórí odi.”

27. Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀ga mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sìí ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odo-ta ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”

28. Nígbà náà aláṣẹ dìdé ó sì pè jáde ní èdè Hébérù pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Ásìría!

29. Èyí ni ohun tí ọba sọ: má ṣe jẹ́ kí Héṣékíáyà tàn ọ́ jẹ kò le gbà ọ́ kúrò ní ọwọ́ mi

30. Má se jẹ́ kí Héṣékíáyà tì ọ́ láti gbàgbọ́ nínú Olúwa nípa sísọ pé, ‘Olúwa yóò gbà wá nítòótọ́; ìlú yìí ni wọn kò ní fi lé ọba ìlú Ásíríà lọ́wọ́.’

31. “Má ṣe tẹ́tí sí Héṣékíáyà. Èyí ni ohun tí ọba Ásíríà sọ: ‘Ṣe àlàáfíà pẹ̀lú mi kí o sì jáde wá sí ọ̀dọ̀ sí mi.’ Nígbà náà olúkúlùkù yín yóò jẹun láti inú àjàrà rẹ̀ àti igi ọ̀pọ̀tọ́, yóò sì mumi láti inú àmù rẹ̀,

32. Títí tí èmi yóò fi wá mú ọ lọ sí ilé gẹ́gẹ́ bí i tìrẹ, ilẹ̀ ọkà àti ọtí wáìnì, ilẹ̀ ouńjẹ àti ọgbà àjàrà, ilẹ̀ òróró ólífì àti ti ilẹ̀ oyin; yàn ìye má sì ṣe yàn ikú!“Kí ẹ má ṣe gbọ́ tí Heṣekáyà, nítorí ó ń tàn yín tí ó ba tí wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá?’

33. Ṣé òrìṣà àwọn orílẹ̀ èdè kankan ti gba ilé rẹ lọ́wọ́ àwọn ọba Ásíríà?

34. Níbo ni àwọn òrìṣà Hámátì àti Árípádì gbé wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Ṣérárifáímù, Hẹ́nà àti ífà gbé wà? Wọ́n ha gba Ṣámáríà kúrò lọ́wọ́ mi bí?

35. Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà ilẹ̀ yìí tí ó ti gbìyànjú láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa yóò ṣe gba Jérúsálẹ́mù kúrò lọ́wọ́ mi?”

36. Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ènìyàn náà dákẹ́ síbẹ̀ wọn kò sì sọ ohunkóhun, láti fi fèsì, nítorí ọba ti paláṣẹ, “Ẹ má ṣe dáa lóhùn.”

37. Nígbà náà Élíákímù ọmọ Hílíkíyà olùtọ́jú ààfin, Séríbù akọ̀wé àti Jóà ọmọ Ásáfù akọ̀wé ránsẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Héṣékíáyà, pẹ̀lú aṣọ wọn yíya, ó sì wí fún un ohun tí olùdárí pápá ti sọ.