orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Fífi Ayọ̀ Wọlé

1. Bí wọ́n ti sún mọ́ Jérúsalẹmu, tí wọ́n dé ìtòòsí ìlú Bẹ́tífágè ní orí òkè Ólífì, Jésù sì rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì,

2. Ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí ìletò tó wà ni tòòsí yín, ẹ̀yin yóò rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ti wọ́n so pẹ̀lú ọmọ rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Ẹ tú wọn, kí ẹ sì mú wọn wá fún mi.

3. Bí ẹnikẹ́ni bá sì béèrè ìdí tí ẹ fi ń ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ sáà wí pé, Olúwa ní wọn-ọ́n lò, òun yóò sì rán wọn lọ.”

4. Èyí ṣẹlẹ̀ láti mú àsọtẹ́lẹ̀ wòlíì ṣẹ pé:

5. “Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Síónì pé,‘Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,ní ìrẹ̀lẹ̀, ó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,àti lórí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.’ ”

6. Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà sí lọ, wọ́n ṣe bí Jésù ti sọ fún wọn

7. Wọ́n sì mú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà pẹ̀lú ọmọ rẹ̀, wọ́n tẹ́ aṣọ lé e, Jésù si jókòó lórí rẹ̀.

8. Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì tẹ́ aṣọ wọn sí ojú ọ̀nà níwájú rẹ̀, ẹlòmíràn sẹ́ ẹ̀ka igi wẹ́wẹ́ wọ́n sì tẹ́ wọn sí ojú ọ̀nà.

9. Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń lọ níwájú rẹ̀ àti lẹ́yìn rẹ̀ pẹ̀lú ń kígbe pé,“Hòsánà fún ọmọ Dáfídì!”“Olùbùkún ni fún ẹni tí ó ń bọ̀ ní orúkọ Olúwa!”“Hòsánà ní ibi gíga jùlọ!”

10. Bí Jésù sì ti ń wọ Jerúsálémù, gbogbo ìlú mì tìtì, àwọn ènìyàn bẹ̀rẹ̀ sí í bi ara wọn pé, “Ta nì yìí?”

11. Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì dáhùn pé, “Èyí ni Jésù, wòlíì náà láti Násárẹ́tì ti Gálílì.”

Jésù Palẹ̀ Tẹ́ḿpìlì Mọ́

12. Jésù sì wọ inú tẹ́ḿpì Ọlọ́run. Ó sì lé àwọn ti ń tà àti àwọn ń rà níbẹ̀ jáde. Ó yí tábìlì àwọn onípàsípààrọ̀ owó dànù, àti tábìlì àwọn tí ó ń ta ẹyẹlẹ́.

13. Ó wí fún wọn pé, “A sáà ti kọ ọ́ pé, ‘Ilé àdúrà ni a ó máa pe ilé mi’, ṣùgbọn ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ibùdó àwọn ọlọ́ṣà.”

14. A sì mú àwọn afọ́jú àti àwọn arọ wá sọ́dọ̀ rẹ̀ ní tẹ̀ḿpìlì, ó sì mú wọ́n láradá

15. Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin rí àwọn iṣẹ́ ìyanu ńlá wọ̀nyí, ti wọ́n sì tún ń gbọ́ tí àwọn ọmọdé ń kigbé nínú tẹ́ḿpìlì pé, “Hòsánà fún ọmọ Dáfídì,” inú bí wọn.

16. Wọ́n sì bí i pé, “Ǹjẹ́ ìwọ gbọ́ nǹkan tí àwọn ọmọdé wọ̀nyí ń sọ?”Jésù sí dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni,”“Àbí ẹ̀yin kò kà á pé ‘Láti ẹnu àwọn ọmọdé àti àwọn ọmọ-ọmú,ni a ó ti máa yìn mí’?”

17. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀, ó lọ sí Bẹ́tánì. Níbẹ̀ ni ó dúró ní òru náà.

Igi Ọ̀pọ̀tọ̀ Gbẹ

18. Ní òwúrọ̀ bí ó ṣe ń padà sí ìlú, ebi ń pa á.

19. Ó sì ṣàkíyèsí igi ọ̀pọ̀tọ́ kan lẹ́bàá ojú ọ̀nà, ó sì lọ wò ó bóyá àwọn èso wà lórí rẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹyọ kan, ewé nìkan ni ó wà lórí rẹ̀. Nígbà náà ni ó sì wí fún igi náà pé, “Kí èso má tún so lórí rẹ mọ́.” Lójú kan náà igi ọ̀pọ̀tọ́ náà sì gbẹ.

20. Nígbà tí àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ rí èyí, ẹnú yà wọn, wọ́n béèrè pé, “Báwo ni igi ọ̀pọ̀tọ́ náà ṣe gbẹ kíákíà?”

21. Jésù wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí ẹ̀yin bá lè ní ìgbàgbọ́ láì síyè méjì, nígbà náà ẹ̀yin yóò lè ṣe irú tí a se sí igi ọ̀pọ̀tọ́, Ẹ̀yin yóò lè sọ fún òkè yìí pé, ‘Yí ipò padà sínú òkun,’ yóò sì ríbẹ́ẹ̀.

22. Bí ẹ̀yin bá gbàgbọ́, ẹ̀yin lè rí ohunkóhun tí ẹ bá béèrè nínú àdúrà gbà.”

A béèrè àṣẹ tí Jésù ń lò

23. Jésù wọ tẹ̀ḿpìlì, nígbà tí ó ń kọ́ni, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn àgbààgbà Júù tọ̀ ọ́ wá. Wọ́n béèrè pé “nípa àṣẹ wo ni o fi ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí? Ta ni ó sì fún ọ ni àsẹ yìí?”

24. Jésù sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èmi yóò si bí yin léère ohun kan pàtọ́, bí ẹ̀yin bá lé sọ fún mi, nígbà náà èmi yóò sọ fún yín, àṣẹ tí Èmi fi ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí.

25. Níbo ni ìtẹ̀bọmi Jóhànù ti wa? Láti ọ̀run wá ni, tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn.”Wọ́n sì bá ara wọn gbèrò pé, “Bí àwa bá wí pé láti ọ̀run wá ni, òun yóò wí fún wa pé, ‘È é ha ti ṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà á gbọ́?’

26. Ní ìdà kejì, bí àwa bá sì sọ pé, ‘Láti ọ̀dọ̀ ènìyàn,’ àwa bẹ̀rù ìjọ ènìyàn, nítorí gbogbo wọ́n ka Johanu sí wòlíì.”

27. Nítorí náà wọ́n sì dáhùn pé, “Àwa kò mọ̀.”Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí èyí, èmi kò ní sọ àṣẹ tí èmi fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí fún yín.

Òwe Àwọn Ọmọ Méjì

28. “Kí ni ẹ rò nípa eléyìí? Ọkùnrin kan ti ó ní àwọn ọmọkùnrin méjì. Ó sọ fún èyí ẹ̀gbọ́n pé, ‘Ọmọ, lọ ṣíṣẹ́ nínú ọgbà àjàrà lónìí.’

29. “Ó sì dá baba rẹ̀ lóhùn pé, ‘Èmi kò ní í lọ,’ ṣùgbọ́n níkẹyìn ó yí ọkàn padà, ó sì lọ.

30. “Nígbà náà ni baba yìí tún sọ fún èyi àbúrò pé, ‘Lọ ṣiṣẹ́ ní oko.’ Ọmọ náà sì sọ pé, ‘Èmi yóò lọ, baba,’ ṣùgbọ́n kò lọ rárá.

31. “Nínú àwọn méjèèjì yìí, èwo ni ó ṣe ìfẹ́ baba wọn?”Gbogbo wọn sì fohùn ṣọ̀kan pé, “Èyí ẹ̀gbọ́n ni.”Jésù wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, àwọn agbowó-òde àti àwọn panṣágà yóò wọ ìjọba ọ̀run ṣíwájú yín.

32. Nítorí Jòhánù tọ́ yin wá láti fi ọ̀nà òdodo hàn yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbà á gbọ́, ṣùgbọ́n àwọn agbowó-òde àti àwọn panṣágà ronúpìwàdà, bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ rí àwọn ohun tí ń ṣẹlẹ̀ wọ̀nyí, ẹ kọ̀ láti ronúpìwàdà, ẹ kò gbà á gbọ́.”

Òwe Àwọn Ayálégbé

33. “Ẹ gbọ́ òwe mìíràn: Baálé ilé kan tí ó gbin àjàrà, ó ṣe ọgbà yìí ká, ó wá ibi ifúntí sínú rẹ̀, ó kọ́ ilé-ìsọ́. Ó sì fi oko náà ṣe àgbàtọ́jú fún àwọn àgbẹ̀ kan, ó sì lọ sí ìrìnàjò.

34. Nígbà ti àkókò ìkórè súnmọ́, ó rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sí àwọn àgbẹ̀ náà láti gba èyí ti ó jẹ tirẹ̀ wá.

35. “Ṣùgbọ́n àwọn olágbàtọ́jú sì mú àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọn lu ẹnì kínní, wọn pa èkèjì, wọ́n si sọ ẹ̀kẹ́ta ní òkúta.

36. Lẹ́ẹ̀kejì, ó rán àwọn ìránṣẹ́ tí ó pọ̀ ju ti ìṣaájú sí wọn. Wọ́n sì tún ṣe bí ti àkọ́kọ́ sí àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú.

37. Níkẹyìn, baálé ilé yìí rán ọmọ rẹ̀ pàápàá sí wọn. Ó wí pé, ‘Wọn yóò bu ọlá fún ọmọ mi.’

38. “Ṣùgbọ́n bí àwọn alágbàtọ́jú wọ̀nyí ti rí ọmọ náà lókèèrè, wọ́n wí fún ara wọn pé, ‘Èyí ni àrólé náà. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, kí a sì jogún rẹ̀.’

39. Wọ́n sì wọ́ ọ jáde kúrò nínú ọgbà, wọ́n sì pa á.

40. “Nítorí náà kí ni ẹ ní èrò wí pé olóko náa yóò ṣe pẹ̀lú àwọn alágbàtọ́jú wọ̀nyí nígbà tí ó bá padà dé?”

41. Wọ́n wí pé, “Òun yóò pa àwọn ènìyàn búburú náà run, ní ipò òsì, yóò sì fi ọgbà àjàrà rẹ̀ fún àwọn alágbàtọ́jú mìíràn tí yóò fún un ní èso tirẹ̀ lásìkò ìkórè.”

42. Jésù wí fún wọ́n pé, “Àbí ẹ̀yin kò kà á nínú ìwé Mímọ́ pé:“ ‘Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀ sílẹ̀,ni ó di pàtàkì igun ilé;Iṣẹ́ Olúwa ni èyí,ó sì jẹ́ ìyanu ní ojú wa’?

43. “Nítorí náà èmi wí fún yín, a ó gba ìjọba Ọlọ́run lọ́wọ́ yín, a ó sì fi fún àwọn ẹlòmíràn tí yóò máa mú èso rẹ̀ wá.

44. Ẹni tí ó bá ṣubú lu òkúta yìí yóò di fífọ́, ṣùgbọ́n ẹni tí òun bá ṣubú lù yóò lọ̀ ọ́ lúúlúú.”

45. Nígbà tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisí gbọ́ òwe Jésù, wọ́n mọ̀ wí pé ó ń sọ̀rọ̀ nípa àwọn.

46. Wọn wá ọ̀nà láti mú un, ṣùgbọ́n wọn bẹ̀rù ọ̀pọ̀ ènìyàn tí wọ́n gba Jésù gẹ́gẹ́ bí wòlíì.