orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ìparun Áì

1. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Jóṣúà pé, “Má ṣe bẹ̀rù, kí àyà kí ó má ṣe fò ọ́. Kó gbogbo àwọn ọmọ ogun pẹ̀lúù rẹ, kí ẹ gòkè lọ gbógun ti Áì. Nítorí mo ti fi ọba Áì, àwọn ènìyàn an rẹ̀, ìlú u rẹ̀ àti ilẹ̀ ẹ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.

2. Ìwọ yóò sì ṣe sí Áì àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Jẹ́ríkò àti ọba rẹ̀, ohun ìkógun wọn àti ohun ọ̀sìn wọn ni kí ẹ̀yin mú fún ara yín. Rán ènìyàn kí wọ́n ba sí ẹ̀yìn ìlú náà.”

3. Bẹ́ẹ̀ ní Jóṣúà àti gbogbo àwọn ọmọ ogun jáde lọ láti dojú kọ Áì. Ó sì yan ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dógún àwọn ọkùnrin ogun rẹ̀ ti ó yakin, ó sì rán wọn lọ ní òru.

4. Pẹ̀lú àwọn àṣẹ wọ̀nyí: “Ẹ fi etí sílẹ̀ dáadáa. Ẹ ba sí ẹ̀yìn ìlú náà. Ẹ má ṣe jìnnà sí i púpọ̀. Kí gbogbo yín wà ní ìmúra-sílẹ̀.

5. Èmi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lúù mi yóò súnmọ́ ìlú náà; Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà bá jáde sí wa, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ìṣáájú, àwa yóò sì ṣá kúrò níwájú u wọn.

6. Wọn yóò sì lépa wa títí àwa ó fi tàn wọ́n jáde kúrò ní ìlú náà, nítorí tí wọn yóò wí pé, wọ́n ń sá lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ wa gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ṣe ní ìṣáájú. Nítorí náà bí a bá sá kúrò fún wọn,

7. ẹ̀yin yóò dìde kúrò ní ibùba, ẹ ó sì gba ìlú náà. Olúwa Ọlọ́run yín yóò sì fi lé e yín lọ́wọ́.

8. Nígbà tí ẹ bá ti gba ìlú náà, kí ẹ sì ti iná bọ̀ ọ́. Kí ẹ ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ. Mo ti fi àṣẹ fún un yín ná.”

9. Nígbà náà ni Jóṣúà rán wọn lọ. Wọ́n sì lọ sí ibùba, wọ́n sì sùn ní àárin Bétélì àti Áì, ní ìwọ̀-oòrùn Áì. Ṣùgbọ́n Jóṣúà wá dúró pẹ̀lú àwọn ènìyan ní orú ọjọ náà.

10. Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kéjì Jóṣúà kó àwọn ọmọ ogun rẹ̀, òun àti àwọn olórí Ísírẹ́lì, wọ́n wọ́de ogun lọ sí Áì.

11. Gbogbo àwọn ọmọ ogun tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ sì gòkè lọ, wọ́n sì súnmọ́ tòsí ìlú náà, wọ́n sì dé iwájú u rẹ̀. Wọ́n sì pàgọ́ ní ìhà àríwá Áì. Àfonífojì sì wà ní agbede-méjì wọn àti ìlú náà.

12. Jóṣúà sì ti fi bí ẹgbẹ̀rún márùn ún ọmọ ogun pamọ́ sí àárin Bétélì àti Áì, sí ìwọ̀-òòrùn ìlú náà.

13. Wọ́n sì yan àwọn ọmọ ogun sí ipò wọn, gbogbo àwọn tí ó wà ní ibùdó lọ sí àríwá ìlú náà àti àwọn tí ó ṣápamọ́ sí ìwọ̀-òrùn rẹ̀. Ní òru ọjọ́ náà Jóṣúà lọ sí àfonífojì.

14. Nígbà tí ọba Áì rí èyí, òun àti gbogbo ọkùnrin ìlú náà yára jáde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù láti pàdé ogun Ísírẹ́lì ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ aginjù. Ṣùgbọ́n kò mọ̀ pé àwọn kan wà ní ibùba ní ẹ̀yìn ìlú náà.

15. Jóṣúà àti gbogbo àwọn Ísírẹ́lì sì ṣe bí ẹni tí a lé padà níwájú wọn, wọ́n sì ṣá gba ọ̀nà ihà.

16. A sì pe gbogbo àwọn ọkùnrin Áì jọ láti lépa wọn, wọ́n sì lépa Jóṣúa títí wọ́n fi tàn wọ́n jáde nínú ìlú náà.

17. Kò sì ku ọkùnrin kan ní Áì tàbi Bétélì tí kò tẹ̀lé Ísírẹ́lì. Wọ́n sì fi ìlẹ̀kùn ibodè náà sílẹ̀ ní ṣíṣí, wọ́n sì ń lépa àwọn ará Ísírẹ́lì.

18. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Jóṣuà pé, “Na ọ̀kọ̀ tí ó wà lọ́wọ́ ọ rẹ sí Áì, nítorí tí èmi yóò fi ìlú náà lé ọ ní ọwọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Jóṣúà sì na ọ̀kọ̀ ọwọ́ ọ rẹ̀ sí Áì.

19. Bí ó ti ṣe èyí tán, àwọn ọkùnrin tí ó ba sì dìde kánkán kúrò ní ipò wọn, wọ́n sáré ṣíwájú. Wọn wọ ìlú náà, wọ́n gbà á, wọ́n sì yára ti iná bọ̀ ọ́.

20. Àwọn ọkùnrin Áì bojú wo ẹ̀yìn, wọ́n rí èéfín ìlú náà ń gòkè lọ sí ọ̀run, ṣùgbọ́n wọn kò rí, àyè láti sá àsálà lọ sí ibìkan kan, nítorí tí àwọn ará Ísírẹ́lì tí wọ́n tí ń sálọ sí ihà ti yípadà sí àwọn tí ń lépa wọn.

21. Nígbà tí Jóṣúà àti gbogbo àwọn ará Ísírẹ́lì rí i pé àwọn tí ó ba ti gba ìlú náà, tí èéfín ìlú náà sì ń gòkè, wọ́n yí padà wọ́n sì kọlu àwọn ọkùnrin Áì.

22. Àwọn ọmọ ogun tí ó ba náà sì yípadà sí wọn láti inú ìlú náà, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wà ní agbede-méjì àwọn ará Ísírẹ́lì ní ìhà méjèèjì. Ísírẹ́lì sì pa wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì jẹ́ kí ọ̀kan kí ó yè tàbí kí ó ṣálọ nínú un wọn.

23. Ṣùgbọ́n wọ́n mú ọba Áì láàyè, wọ́n sì mu-un tọ Jósúà wá.

24. Nígbà tí Ísírẹ́lì parí pípa àwọn ọkùnrin Áì ní pápá àti ní ihà ní ibi tí wọ́n ti lépa wọn lọ, nígbà tí wọ́n pa gbogbo wọn tan, gbogbo àwọn Ísírẹ̀lì sì padà sí Áì, wọ́n sì pa àwọn tí ó ṣẹ́kù síbẹ̀.

25. Ẹgbẹ̀rún méjìlá ọkùnrin àti obìnrin ni ó kú ní ọjọ́ náà-gbogbo wọn jẹ́ àwọn ènìyàn Áì.

26. Nítorí tí Jósúà kò fa ọwọ́ ọ rẹ̀ tí ó di ọ̀kọ̀ mú sí ẹ̀yìn, títí ó fi pa gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú Áì run.

27. Ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì kó ẹran ọ̀sìn àti ìkógún ti ìlú yìí fún ara wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Jóṣúà.

28. Jóṣúà sì jó Áì, ó sì sọ ọ́ di ààtàn, àní ahoro di òní yìí.

29. Ó sì gbé ọba Áì kọ́ orí igi, ó sì fi kalẹ̀ síbẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́. Bí òòrùn sì ti wọ̀ ni Jóṣúà pàṣẹ fún wọn láti sọ òkú rẹ̀ kalẹ̀ kúrò ní orí igi, kí wọn sì wọ́ ọ jù sí àtiwọ ẹnu ibodè ìlú náà. Wọ́n sì kó òkítì òkúta ńlá lé e ní orí, èyí tí ó wà títí di òní yìí.

Májẹ̀mu tí a sọ di ọ̀tun ní orí òkè Ébálì

30. Nígbà náà ni Jóṣúà mọ pẹpẹ kan fún Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì, ní òkè Ébálì,

31. gẹ́gẹ́ bí Móṣè ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Ó sì kọ́ ọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú Iwé Òfin Móṣè, pẹpẹ odindi òkúta, èyí tí ẹnìkan kò fi ohun èlò irin kàn rí. Wọ́n sì rú ọrẹ ẹbo ṣísun àti ọrẹ àlàáfíà ní orí i rẹ̀ sí Olúwa.

32. Níbẹ̀ ní ojú àwọn ará Ísírẹ́lì, Jósúà sì ṣe àdàkọ òfin Mósè èyí tí ó ti kọ sí ara òkúta náà.

33. Gbogbo Ísírẹ́lì, àlejò àti ọmọ ìlú, pẹ̀lú àwọn àgbà, olórí àti onídàájọ́ dúró ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àpótí ẹ̀rí Olúwa tí ó kọjú sí àwọn àlùfáà tí ó rù ú, tí wọ́n jẹ́ ọmọ Léfì. Ìdajì àwọn ènìyàn náà dúró ní Òkè Gérísímù, àwọn ìdajì si dúró ni òkè Ébálì, gẹ́gẹ́ bí Mósè ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ rí, pé kí wọn súre fún àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì.

34. Lẹ́yìn èyí, Jóṣúà sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin ìbùkún àti ègún-gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú Ìwé Òfin.

35. Kò sí ọ̀rọ̀ kan nínú gbogbo èyí tí Mósè pàṣẹ, tí Jósúà kò kà ní iwájú gbogbo àjọ Ísírẹ́lì, títí fi kan àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wọn, àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárin wọn.