orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Àwọn Ìlú Ààbò.

1. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Jósúà pé,

2. “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mósè,

3. kí ẹni tí ó bá sèèsì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀ọ́mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.

4. “Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbààgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàárin wọn.

5. Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa wọn, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí.

6. Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń siṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”

7. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedésì ní Gálílì ní ìlú òkè Náfítanì, Sékémù ní ìlú òkè Éfúráímù, àti Kíríátì aginjù (tí í ṣe, Hébúrónì) ní ìlú òkè Júdà.

8. Ní ìhà ìlà oòrùn Jọ́dánì ti Jẹ́ríkò, wọ́n ya Bésẹ́rìù ní aṣalẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Rúbẹ́nì, Rámótì ní Gílíádì ní ẹ̀yà Gádì, àti Golanì ní Básánì ní ẹ̀yà Mánásè.

9. Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tàbí àlejò tí ń gbé ní àárin wọn tí ó sèèsì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.