orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ikú Àwọn Àkọ́bí

1. Nísínsìn yìí, Olúwa sọ fún Mósè pé èmi yóò mú ìyọnu kan sí i wá sí orí Fáráò àti ilẹ̀ Éjíbítì. Lẹ́yìn náà yóò jẹ́ kí ẹ̀yín kí ó lọ kúrò níhín yìí, nígbà tí ó bá sì ṣe bẹ́ẹ̀ yóò lé yín jáde pátápátá.

2. Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé kí tọkùnrin tobìnrin wọn béèrè fún ohun èlò fàdákà àti wúrà lọ́wọ́ aládùúgbò rẹ̀.

3. (Olúwa jẹ́ kí wọn rí ojú rere àwọn ará Éjíbítì, pàápàá, Mósè fún ra rẹ̀ di ènìyàn pàtàkì ní ilẹ̀ Éjíbítì ní iwájú àwọn ìjòyè Fáráò àti ní iwájú àwọn ènìyàn pẹ̀lú).

4. Nígbà náà ni Mósè wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Ní ọ̀gànjọ́ òru èmi yóò la ilẹ̀ Éjíbítì kọjá.

5. Gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin tí ó wà ní ilẹ̀ Éjíbítì ni yóò kú, bẹ̀rẹ̀ lórí àkọ́bí ọkùnrin Fáráò tí ó jòkòó lórí ìtẹ́ rẹ̀, tí ó fi dé orí àkọ́bí ọmọkùnrin ti ẹrú-bìnrin tí ń lọ ọlọ àti gbogbo àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.

6. Igbe ẹkún ńlá yóò sọ jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Éjíbítì. Irú ohun búburú tí kò sẹlẹ̀ rí tí kò sí tún ni sẹlẹ̀ mọ́.

7. Ṣùgbọ́n láàrin àwọn ará Ísírẹ́lì ajá lásán kò ní gbó àwọn ènìyàn tàbí àwọn ẹran wọn.’ Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti fi ìyàtọ̀ sáàrín àwọn ará Éjíbítì àti Ísírẹ́lì.

8. Gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ wọ̀nyí yóò tọ̀ mí wá, wọn yóò wólẹ̀ ni iwájú, mi wọn yóò sì máa wí pé, ‘Lọ àti àwọn ènìyàn tí ó tẹ̀ lé ọ!’ Lẹ́yìn náà èmi yóò jáde.” Nígbà náà ni Mósè fi ìbínú jáde kúrò ní iwájú Fáráò

9. Olúwa ti sọ fún Mósè pé, “Fáráò yóò kọ̀ láti fetí sílẹ̀ sí ọ kí iṣẹ́ ìyanu mí le pọ̀ sí ní Éjíbítì.”

10. Mósè àti Árónì ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu wọ̀nyí níwájú Fáráò, ṣùgbọ́n Olúwa sé ọkàn Fáráò le, òun kò sí jẹ́ kí àwọn Ísírẹ́lì jáde kúrò ni orílẹ̀ èdè rẹ̀.