orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Àwọn Òwe Mìíràn Ti Sólómónì

1. Wọ̀nyí ni àwọn òwé mìíràn tí Sólómónì pa, tí àwọn ọkùnrin Hẹsikáyà ọba Júdà dà kọ.

2. Ògo Olúwa ní láti fi ọ̀rọ̀ kan pamọ́;láti rí ìdí ọ̀rọ̀ kan ni ògo àwọn ọba.

3. Bí ọ̀run ṣe ga tó tí ayé sì jìnbẹ́ẹ̀ ni ó ṣòro láti mọ èrò ọkàn ọba.

4. Mú ìdàrọ́ kúrò lára fàdákàohun èlò yóò sì jáde fún alágbẹ̀dẹ fàdákà

5. mú ènìyàn búburú kúrò níwájú ọbaa ó sì fìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ nípaṣẹ̀ òdodo.

6. Má ṣe gbé ara rẹ ga níwájú ọba,má sì ṣe jìjàdù ààyè láàrin àwọn ènìyàn pàtàkì

7. Ó sàn kí ó wí fún ọ pé, “Gòkè wá síhìn ín”ju wí pé kí ó dójú tì ọ́ níwájú ènìyàn pàtàkì.

8. Ohun tí o ti fi ojú ara rẹ rímá ṣe kánjú gbé e lọ sílé ẹjọ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe ní ìgbẹ̀yìnbí aládùúgbò rẹ bá dójú tì ọ́?

9. Bí o bá ń ṣe àwíjàre rẹ níwájú aládùúgbò rẹ,má ṣe tú àsírí tí ẹlòmíràn ní lọ́dọ̀ rẹ,

10. àìṣe bẹ́ẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ le dójú tì ọ́orúkọ burúkú tí ìwọ bá sì gba kì yóò tán láéláé.

11. Ọ̀rọ̀ tí a sọ ní àkókò tí ó yẹó dàbí èṣo wúrà nínú àpẹẹrẹ fàdákà.

12. Bí i yẹtí wúrà tàbí ohun ọ̀ṣọ́ ti wúrà dáradárani ìbáwí ọlọ́gbọ́n fún etí tí ó bá fetísílẹ̀.

13. Bí títutù òjò yìnyín ní àsíkò ìkórèni ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olóòtọ́ sí àwọn tí ó rán anó ń tu ọ̀gá rẹ̀ nínú.

14. Bí ojú ṣíṣú àti afẹ́fẹ́ láì sí òjòni ènìyàn tí ń yangàn nípa ẹ̀bùn tí kò fún ni.

15. Nípa ṣùúrù a lè yí ọba lọ́kàn padàahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ rírọ̀ sí egungun.

16. Bí ìwọ bá rí oyin, jẹ ẹ́ ní ìwọ̀nbabí o bá jẹ ẹ́ jù, ìwọ yóò sì bì í.

17. Má ṣe máa lọ sí ilé aládùúgbò rẹ nígbà gbogbotàbí kí ó máa lọ ṣíbẹ̀ lálọ jù, yóò sì kórìíra rẹ.

18. Bí àdá, idà tàbí ọ̀kọ̀ tí ó múni ènìyàn tí ó jẹ́rìí èké lòdì sí aládùúgbò rẹ̀.

19. Bí eyín tí ó bàjẹ́ tàbí ẹṣẹ̀ tí ó rọni ìgbẹ́kẹ̀lé lórí aláìṣòótọ́ ní àsìkò ìdàámú.

20. Bí ẹni tí ó bọ́ra kalẹ̀ ní ọjọ́ tí òtútù mú,tàbí iyọ̀ tí a fi ra ojú egbò ọgbẹ́ tàbí bí ọtí kíkan tí a dà sórí sódàní ẹni tí ń kọ orin sí ọkàn tí ó bàjẹ́.

21. Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ jẹ;bí òrùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mú.

22. Nípa ṣíṣe báyìí, ìwọ yóò wa ẹ̀yín iná lé e lórí Olúwa yóò sì san ọẹ̀san rẹ̀ fún ọ.

23. Bí afẹ́fẹ́ gúṣù ti í mú òjò wá,bí ahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀yìn ṣe ń mú ojú ìbínú wá.

24. Ó sàn láti gbé ní ibi igun kan lórí òrùléju láti bá aya oníjà gbé ilé pọ̀.

25. Bí omi tútù sí ẹni tí òrùngbẹ ń gbẹni ìròyìn ayọ̀ láti ọ̀nà jíjìn.

26. Bí ìsun tí ó di àbàtà tàbí kanga tí omi rẹ̀ bàjẹ́ni olódodo tí ó fi àyè gba ènìyàn búburú.

27. Kò dára láti jẹ oyin àjẹjù,bẹ́ẹ̀ ni kò pọ́nni lé láti máa wá ọlá fún ara ẹni.