orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 2 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ọlọ́run Gbà Fún Sàtánì Kí Ó Dán Jóòbù Wò Lẹ́ẹ̀kejì

1. Ó sì tún di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá síwájú Olúwa, Sàtánì sì wá pẹ̀lú wọn láti pe níwájú Olúwa.

2. Olúwa sì bi Sàtánì pé, Níbo ni ìwọ ti wá?Sàtánì sì dá Olúwa lóhùn pé, “Láti lọ síwá sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”

3. Olúwa sì wí fún Sàtánì pé, “Ìwọ ha kíyèsí Jóòbù ìránṣẹ́ mi, pé, kò sí èkejì rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí ń ṣe olóòótọ́ tí ó sì dúró sinsin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì kóríra ìwà búburú, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di ìwà òtítọ́ rẹ̀ mu ṣinṣin, bí ìwọ tilẹ̀ ti dẹ mí sí i láti run-ún láìnídìí.”

4. Sàtánì sì dá Olúwa lóhùn wí pé, “Awọ fún awọ; àní ohun gbogbo tí ènìyàn ní, òun ni yóò fi ra ẹ̀mí rẹ̀.

5. Ṣùgbọ́n nawọ́ rẹ nísinsìn yìí, kí ó tọ́ egungun rẹ̀ àti ara rẹ̀, bí kì yóò sì bọ́hùn ní ojú rẹ.”

6. Olúwa sì wí fún Sàtánì pé, “Wò ó, Ó ń bẹ ní ìkàwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n dá ẹ̀mí rẹ̀ sí.”

7. Bẹ́ẹ̀ ni Sàtánì jáde lọ kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ Jóòbù ní oówo kíkan kíkan láti àtẹ́lẹṣẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀

8. Ó sì mú àpáàdì, ó fi ń ha ara rẹ̀, ó sì jókòó nínú eérú.

9. Nígbà náà ni aya rẹ̀ wí fún-un pé, “Ìwọ di ìwà òtítọ́ mú síbẹ̀! Bú Ọlọ́run, kí ó sì kú!”

10. Ṣùgbọ́n ó dá a lóhùn pé, “Ìwọ sọ̀rọ̀ bí ọ̀kan lára àwọn obìnrin aláìmọ́ye ti í sọ̀rọ̀; há bà! Àwa yóò ha gba ire lọ́wọ́ Ọlọ́run, kí a má sì gba ibi?”Nínú gbogbo èyí, Jóòbù kò fi ètè rẹ̀ ṣẹ̀.

Ọ̀rẹ́ Jóòbù Mẹ́ta

11. Nígbà tí àwọn ọ̀rẹ́ Jóòbù mẹ́ta gbúròó gbogbo ibi tí ó bá a, wọ́n wá, olúkúlùkù láti ibùjókòó rẹ̀; Élífásì, ara Témà àti Bílídádì, ara Ṣúà, àti Sófárì, ará Náámù: nítorí pé wọ́n ti dájọ́ ìpàdé pọ̀ láti bá a sọ̀fọ̀ àti láti sìpẹ̀ fún un.

12. Nígbà tí wọ́n gbójú wọn wò ní òkèrè réré, tí wọ́n kò sì mọ̀ ọ́n, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sọkún: olúkúlùkù sì fa àṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, wọ́n sì ku erùpẹ̀ sí ojú ọ̀run, wọ́n sì tẹ́ orí gbà á.

13. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n jòkòó tì í ní inú erùpẹ̀ ní ọjọ́ méje ti ọ̀sán ti òru, ẹnikẹ́ni kò sì bá a dá ọ̀rọ̀ kan sọ nítorí tí wọ́n ti rí i pé ìbànújẹ́ rẹ̀ pọ̀ gidigidi.