orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ìdáhùn Jóòbù

1. Ṣùgbọ́n Jóòbù sì dáhùn wí pé:

2. Báwo ni ìwọ ń ṣe ìrànlọ́wọ́ ẹni tíkò ní ipá, báwo ní ìwọ ń ṣe gbà apá ẹni tí kò ní agbára?

3. Báwo ni ìwọ ń ṣe ìgbìmọ̀ ẹni tí kòní ọgbọ́n, tàbí báwo ní ìwọ sọdi ọ̀ràn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ bí ó ti rí?

4. Ta ni ó ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ àwọnọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti ẹ̀mi ta ni ó gba ẹnu rẹ sọ̀rọ̀?

5. “Àwọn aláìlágbára ti iṣà òkúwárìrì, lábẹ́ omi pẹ̀lú àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

6. Ìhòòhò ni ipò òkú níwájú Ọlọ́run,ibi ìparun kò sí ní ibojì.

7. Òun ní o nà ìhà àríwá ọ̀run ní ibiòfùrufú, ó sì fi ayé rọ̀ ní ojú òfo.

8. Ó di omi pọ̀ nínú ìkùùkù àwọsánmọ̀rẹ̀ tí ó nípọn; àwọsánmọ̀ kò sì ya nísàlẹ̀ wọn.

9. Ó sì fa ojú ìtẹ́ rẹ̀ sẹ́yìn, ó sì tẹàwọsánmọ̀ rẹ̀ sí i lórí.

10. Ó fi idẹ yí omi òkun ká, títí déààlà ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn.

11. Ọ̀wọ̀n òpó ọ̀run wárìrì, ẹnu sì yàwọ́n sì ìbàwí rẹ̀.

12. Ó fi ipá rẹ̀ dààmú omi òkun; nípaòye rẹ̀, ó gé Ráhábù sí wẹ́ẹ́wẹ́.

13. Nípa ẹ̀mí rẹ̀ ni ó ti ṣe ọ̀run níọ̀sọ́; ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti dá ejò wíwo nì.

14. Kíyèsí i, èyí ní òpin ọ̀nà rẹ̀;ohùn èyí tí a gbọ́ ti kéré tó!Ta ni ẹni náà tí òye àrá agbára rẹ̀ lè yé?”