orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Èsì Élífásásì

1. Ígbà náà ni Élífásì, ará Témà, dáhùn wí pé:

2. “Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run?Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?

3. Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmáarèpé, olódodo ni ìwọ? Tàbí èrèkí ni fún un, ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?

4. “Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rùỌlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?

5. Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi, àti ẹ̀ṣẹ̀rẹ láìníye?

6. Nítòótọ́ ìwọ bèèrè fún ààbò niọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí, ìwọsì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.

7. Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu, ìwọsì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.

8. Bí ó ṣe ti alágbára nì ni, òun ni óní ilẹ̀, ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.

9. Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ níọwọ́ òfo; Apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.

10. Nítorí náà ni ìdẹkùn ṣe yí ọkáàkiri, àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu,

11. Èé ṣe tí òkùnkùn, fi pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ tíìwọ kò fi lè ríran; Èé ṣe tíọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12. “Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run?Ṣá wò orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!

13. Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀?Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?

14. Àwọ̀sánmọ̀ tí ó nípọn ni ìborafún un, tí kò fi lè ríran; ó sì rìn nínú àyíká ọ̀run.

15. Ìwọ fẹ́ rìn ìpa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọnènìyàn búburú tí rìn?

16. A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayéláìpé ọjọ́ wọn; ìpilẹ̀ wọn ti dé bí odò síṣàn;

17. Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé,lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí niOlódùmárè yóò ṣe fún wọn?

18. Ṣíbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn!Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!

19. “Àwọn olódodo rí ìparun wọn,wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ̀ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn ín ẹlẹ́yà pé,

20. Lótìítọ́ àwọn ọ̀ta wa ni a ké kúrò, ináyóò sì jó oró wọn run.

21. “Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sìrí àlàáfíà; Pẹ̀lú rẹ̀ nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.

22. Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀wá, kí o sì tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.

23. Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀Olódùmáarè, a sì gbé ọ ró, bíìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,

24. Tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀lórí erùpẹ̀ àti wúrà ófiri lábẹ́ òkúta odò,

25. Nígbà náà ní Olódùmáarè yóò jẹ́wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

26. Lótìítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inúdídùn nínú Olódùmáarè, ìwọ ósì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.

27. Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀,yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.

28. Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú,yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.

29. Nígbà tí ipa-ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀,nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!

30. Yóò gba ẹni tí kì í iṣe aláìjẹ̀bi là,a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”