orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n àti òye Jóòbù

1. “Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àtiibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.

2. Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.

3. Ènìyàn ni ó parí òkùnkùn, ó sì ṣeàwárí òkúta òkùnkùn àti tiinú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.

4. Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jìn sí àwọn tíń gbé òkè, àwọn tí ẹṣẹ̀ ènìyàngbàgbé; wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.

5. Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,àti ohun tí ó wà ní ìṣàlẹ̀ ni ó yí sókè bí ẹni pé iná.

6. Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Sáfírì, o sìní erùpẹ̀ wúrà.

7. Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojúgúnnugún kò rí i rí;

8. Àwọn ẹrankan agbéraga kò rìn ibẹ̀rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.

9. Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkèńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.

10. Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.

11. Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún—kún-ya, ó sì mú ohun tí ópamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.

12. “Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wáọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?

13. Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.

14. Ọ̀gbun wí pé, kò sí nínú mi;omi òkun sì wí pé, kò si nínú mi.

15. A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kòle è fi òsùnwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.

16. A kò le è fi wúrà Ófírì, tàbíòkútà Óníkísì iyebíye, tàbí òkúta Sáfírì díye lé e.

17. Góòlù àti òkúta Kírísítalì kò tóẹgbẹ́rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èló wúrà ṣe pàsípààrọ̀ rẹ̀.

18. A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta Jásípérì;iye ọgbọ́n sì ju òkúta Rubì lọ.

19. Òkùta tópásì ti Kúsì kò tóẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.

20. “Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?Tàbí níbo ni òye ń gbé?

21. A rí i pé, ó farasinko kúrò ní ojúàwọn alààyè gbogbo, ó sì fara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.

22. Ibi ìparun (Ábádónì) àti ikú wípé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.

23. Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nàrẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé

24. Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ósì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,

25. Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fiòṣùwọ̀n wọ̀n omi.

26. Nígbà tí ó pàsẹ fún òjò, tí ó sì laọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,

27. Nígbà náà ni órí i, ó sì sọ ọ́ jáde;ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.

28. Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,‘Kíyè sí i ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àtiláti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.’ ”