orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Élíhù Pe Jóòbù Níjà

1. Nígbà náà ni Élíhù dáhùn, ó sì wí pé:

2. “Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.

3. Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò,bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.

4. Ẹ jẹ́ kí a ṣà ẹ̀tọ́ yàn fún ara wa;ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrin wa.

5. “Nítorí pé Jóòbù wí pé, ‘Aláìlẹ́sẹ̀ ni èmi;Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.

6. Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí,bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò níàwòtán dídì ọgbẹ́.’

7. Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jóòbù,tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?

8. Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ósì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.

9. Nítorí ó sá ti wí pé,‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn,tí yóò fí máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’

10. “Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetí sílẹ̀ sí miẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye:Ódodi fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú àti fúnOlódùmárè, tí yóò fí ṣe àìṣedéédéé!

11. Nítorí pé ó ń sá fún ènìyàn fúnohun tí a bá ṣe, yóò sì múolúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.

12. Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkúwà;bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.

13. Ta ni ó yàn ań lórí, tàbí ta ni ófi gbogbo ayé lée lọ́wọ́?

14. Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,

15. gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀,ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.

16. “Ǹjẹ́ nisinsìnyí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí;fetísí ohùn ẹnu mi.

17. Ẹni tí ó kóríra òtítọ́ ha le iṣe olóríbí? Ìwọ ó hà sì dá olóótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?

18. O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ènìyàn búburú ní ìwọ,tàbí fún àwọn ọmọ aládé pé, ìkà ni ẹ̀yin;

19. Ańbọ̀tórí fún ẹni tí kì í ṣójúṣàájú àwọn ọmọ-aládétàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí talákà lọ.Nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?

20. Ní ìṣẹ́jú kán ni wọn ó kú, láàrin ọ̀gànjọ́àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́, wọn a sì kọjá lọ;A sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.

21. “Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa-ọ̀nàènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.

22. Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí ojìjìikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.

23. Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsíẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọsínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.

24. Òun ó sì fọ́ àwọn alágbáratúútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmìíràn dípò wọn,

25. nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yíwọn po ní òru; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ́rẹ́ pọ̀.

26. Ó kọlù wọ́n nítorí ìwàbúburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmìíràn rí i,

27. nítorí pé wọ́n padà sẹ́yìndà sí i,wọn kò sì fi yè sí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,

28. kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkúnàwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òunsì gbọ́ igbe ẹkún aláìní

29. ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bápa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i?Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe é orilẹ̀ èdè tàbi sí ènìyàn kan ṣoṣo;

30. Kí àgàbàgebè kí ó má báà jọbakí wọn kí ó má di ìdẹ̀wò fún ènìyàn.

31. “Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fúnỌlọ́run pé, èmi jẹ̀bí; èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?

32. Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bimo bá sì dẹ́sẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.

33. Íṣe bí ti inú rẹ̀ pe òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà?Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bíìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́ tàbíìwọ ìbá fẹ́ kì í ṣe èmi; Pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ!

34. “Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fúnmi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,

35. ‘Jóòbù ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣealáìgbọ́n.’

36. Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jóòbù wò déòpin, nítorí ìdahùn rẹ̀ dà bí i ti ènìyàn búburú:

37. Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ópàtẹ́wọ́ ní àárin wa, ó sì sọọ̀rọ̀ di púpọ̀ sí Ọlọ́run.”