1. Elíhù sì tún sọ̀rọ̀ wí pé:
2. “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fi hàn ọ́nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
3. Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jínjìn wá,èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
4. Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèkénítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
5. “Kíyèsí i, Ọlọ́run ni alágbára, kò sìgàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
6. Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú síṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
7. Òun kì ímú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́nwà lórí ìtẹ́; Àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
8. Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí asì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
9. Nígbà náà ni o ń sọ àwọn ohun tíwọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ́lú ìgbéraga wọn.
10. Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ósì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedéédéé.
11. Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀ra, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
12. Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
13. “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní àyékó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá dà wọ́n.
14. Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú níèwe, ẹ̀mí wọn a sì wà nínú àwọn oníwà Sódómù.
15. Òun gba òtòsì nínú ìpọ́njú wọn,a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínu ìnira wọn.
16. “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó sì dè ọ lọ látiinú ìhágágá síbi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálànínú rẹ̀ ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ a jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
17. Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọnbúburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
18. Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹmáa bàà tàn ọ́; láti jẹ́ kí títóbi èyà mú ọ sìnà.
19. Ọ̀rọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fidé bá ọ bí? Tàbi ipa agbára rẹ?
20. Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń kéàwọn orilẹ̀ èdè kúrò ní ipò wọn.
21. Máa sọra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀padà sí búrubú; Nítori èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
22. “Kíyèsí i, Ọlọ́run á gbé-ni-ga nípaagbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí òun?
23. Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un,tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
24. Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,ti ènìyàn ni yín nínú orin.
25. Olúkúlùkù a máa rí i; ènìyàn amáa wòó ní òkèrè,
26. Kíyèsí i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sìmọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
27. “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omiọjọ́ sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní odò,
28. tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀, tí ó sì fi ńgbìn lọ́pọ̀lọpọ̀ lórí ènìyàn.
29. Pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni lè imọ́ ìtànkáàwọ̀sánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
30. Kíyèsí i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
31. Nitorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́àwọn orílè èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
32. Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèje ó sìrán sí ẹni olódì.
33. Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!