orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Pẹ̀lúpẹ̀lú Jóòbù sì tún sọ kún ọ̀rọ̀ òwe rẹ̀, ó sì wí pé:

2. “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, ẹni tí ógba ìdájọ́ mi lọ, àti Olódùmárè tí ó bà mi ní ọkàn jẹ́;

3. (Níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀mí mi ń bẹ nínúmi, àti tí ẹ̀mi Ọlọ́run ń bẹ nínú ihò imú mi.)

4. Ètè mi kì yóò sọ̀rọ̀ èké, Bẹ́ẹ̀ niahọ́n mi kì yóò sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.

5. Kí a má ríi pé èmi ń dá yín láre;títí èmi ó fi kú, èmi kì yóò sí ìwà òtítọ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi.

6. Òdodo mi ni èmi dìmú ṣinṣin,èmi kì yóò sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́; àyàmi kì yóò sì gan ọjọ́ kan nínú ọjọ́ ayé mi.

7. “Kí ọ̀ta mi kí ó dàbí ènìyànbúburú, àti ẹni tí ń dìde sími kí ó dàbí ẹni aláìsòdodo.

8. Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè,nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?

9. Ọlọ́run yóò ha gbọ́ àdúrà rẹ̀,nígbà tí ìpọ́jú bá dé sí i?

10. Òun ha le ní inú dídùn sí Olódùmarè?Òun ha lé máa képe Ọlọ́run nígbà gbogbo?

11. “Èmi ó kọ́ yín ní ẹ̀kọ́ ní ti ọwọ́ Ọlọ́run:ọ̀nà tí ńbẹ lọ́dọ̀Olódùmarè ni èmi kì yóò fi pamọ́.

12. Kíyèsí i, gbogbo yín ni ó ti rí i;nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe já sí asán pọ̀ bẹ́ẹ̀?

13. “Ẹ̀yin ni ìpín ènìyàn búburú lọ́dọ̀ Ọlọ́run, àti ogún àwọnaninilára, tí wọ́n ó gbà lọ́wọ́ Olódùmáre:

14. Bí àwọn ọmọ rẹ bá di púpọ̀, fúnidà ni; àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ kì yóò yó fún oúnjẹ.

15. Àwọn tí ó kú nínú tirẹ̀ ni a ósìnkú nínú àjàkálẹ̀-àrùn: àwọnopó rẹ̀ kì yóò sì sunkún fún wọn.

16. Bí ó tilẹ̀ kó fàdákà jọ bí erùpẹ̀, tíó sì dá aṣọ jọ bí amọ̀;

17. Àwọn ohun tí ó tò jọ àwọnolóòótọ́ ni yóò lò ó; àwọnaláìṣẹ̀ ni yóò sì pín fàdákà rẹ̀.

18. Òun kọ́ ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí kòkòrò aṣọ,àti bí ahéré tí olùsọ́ kọ́.

19. Ọlọ́rọ̀ yóò dùbúlẹ̀, ṣùgbọ́n òun kìyóò tún ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́; ó síjú rẹ̀, òun kò sì sí.Nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀,gbogbo rẹ̀ a lọ

20. Ẹ̀rù ńlá bàá bí omi ṣíṣàn;ẹ̀fúùfù ńlá jí i gbé lọ ní òru.

21. Ẹ̀fúùfù ìlà oòrùn gbé e lọ, òun sìlọ; àti bí ìjì ńlá ó sì fà á kúrò ní ipò rẹ̀.

22. Nítorí pé Olódùmárè yóò kọ lù ú,kì yóò sì dá a sí; òun ìbá yọ̀ láti sá kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.

23. Àwọn ènìyàn yóò sì ṣápẹ́ sí ilórí, wọn yóò sì ṣe síọ̀ sí i kúrò ní ipò rẹ̀.