orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ọlọ́run Pe Jóòbù Níjà

1. Ígbà náà ní Olúwa dá Jóòbù lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé:

2. “Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìní ìgbirò ṣuìmọ̀ ní òkùnkùn?

3. Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bíọkùnrin nísinsin yìí, nítorí péèmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dámi lóhùn.

4. “Níbo ni ìwọ wà nígbà ti mo fiìpìnlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.

5. Ta ni ó fi ìwọ̀ rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọbá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?

6. Lórí ibo ni a gbé kan ìpìnlẹ̀ rẹ̀mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,

7. Nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀jùmọ̀ Kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn áńgẹ́lì hó ìhó ayọ̀?

8. “Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkunmọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá,

9. Nígbà tí mo fi àwọ sánmọ̀ ṣe aṣọrẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri se ọ̀já ìgbà nú rẹ̀,

10. Nígbà tí mo ṣe òpin fún-un, tímo sì se bèbè àti ìlẹ̀kùn,

11. Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé,kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?

12. “Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbàọjọ́ rẹ̀ wá ìwọ sì mú ìlà oòrùn mọ ipò rẹ̀,

13. Kí ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lègbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?

14. Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdìamọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.

15. A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúròlọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga yóò sì ṣẹ́.

16. “Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí?Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?

17. A ha sílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ ríbí, ìwọ sì rí ilẹ̀kùn òjìji òkú?

18. Ìwọ mòye ibú ayé bí? Sọ bí ìwọbá mọ gbogbo èyí.

19. “Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí óṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,

20. Tí ìwọ í fi mú un lọ síbi àlá rẹ̀, tíìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?

21. Ìwọ mọ èyí, nitorí nígbà náà nia bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.

22. “Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì Sínóò lọ ríbí, kìwọ sì rí ilé ìṣúrà òjò rí,

23. Tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu,dé ọjọ́ ogun àti ìjà?

24. Ọ̀nà wo ǹi ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ńya, tí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?

25. Ta ni ó la ipadò fún ẹkun omi, àtiọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,

26. Láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tíènìyàn kò sí, ní ihà níbi tí ènìyàn kò sí;

27. Láti tẹ́ ilẹ̀ tútù, aṣálẹ̀ àti ẹgàn lọ́rùnláti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?

28. Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bíikùn ìṣẹ ìrì?

29. Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá?Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?

30. Omi di lile bí òkúta, ojú ibú ńlásì dìlù pọ̀.

31. “Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀Píléyádè dáradára? Tàbí ìwọ le tún di Ìràwọ̀ Óríónù?

32. Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Másárótì jáde wá nígbà àkókò wọn?Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Béárì pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?

33. Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run?Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?

34. “Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè déàwọ̀sánmọ̀, kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?

35. Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kíó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ósì wí fún wọn pé, àwa nìyí?

36. Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí ayétàbí tí ó fi òye sínú ọkàn?

37. Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọ̀sánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,

38. Nígbà tí erupẹ̀ di líle, àtiògúlùtú dípò?

39. “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí?Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọ̀rọ̀ kìnnìún lọ́rùn,

40. Nígbà tí wọ́n bá ń mọ́lẹ̀ nínú ihòtí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?