orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóẹ́lì 2 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Àwọn Jagunjagun Eṣú

1. Ẹ fun ìpè ní Ṣíónì,ẹ sì fún ìpè ìdágàrì ní òkè mímọ́ mi.Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì,nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá,nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.

2. Ọjọ́ òkùnkùn àti òkùdù,ọjọ́ ìkùùkù àti òkùnkùn biribiri,bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá:àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé,ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí,bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.

3. Iná ń jó níwájú wọ́n;ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn:ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Édẹ́nì níwájú wọn,àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù;nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.

4. Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin;wọ́n ń ṣe láńkú láńkú lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun

5. Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun niwọn ń fo ní orí òkèbí ariwo ọ̀wọ́ iná tí ń jó koríko gbígbẹ,bí akọni ènìyàn tí a kó jọ fún ogun.

6. Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀:gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.

7. Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára;wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun;olúkúlúkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀,wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.

8. Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò to ẹnìkejì rẹ̀;olúkúlukù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀:nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù ìdàwọn kì yóò gbọgbẹ́.

9. Wọn yóò sáré síwá ṣẹ́yìn ní ìlú;wọn yóò súré lórí odi,wọn yóò gùn orí ilé;wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.

10. Ayé yóò mì níwájú wọn;àwọn ọ̀run yóò wárìrì;òòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn,àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn ṣẹ́yìn.

11. Olúwa yóò sì bú rámu ramùjáde níwájú ogun rẹ̀:nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi;nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ rẹ̀ ṣẹ;nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi;ara ta ni ó lè gbà á?

Fa Ọkàn Rẹ Ya.

12. “Njẹ́ nítorí náà nísínsin yìí,” ni Olúwa wí,“Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi,àti pẹ̀lú ààwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”

13. Ẹ sì fa ọkàn yín ya,kì í sì í ṣe aṣọ yín,ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín,nítorí tí o pọ̀ ní oore ọ̀fẹ́,ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú,ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.

14. Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà,kí o sì ronúpìwàdà,kí ó sì fí ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀;àní ọrẹ jíjẹ àti ọrẹ mímu fún Olúwa Ọlọ́run yín?

15. Ẹ fún ìpè ní Ṣíónì,ẹ ya ààwẹ̀ kan sí mímọ́,ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.

16. Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ,ẹ ya ìjọ sí mímọ́;ẹ pe àwọn àgbà jọ,ẹ kó àwọn ọmọdé jọ,àti àwọn tí mú ọmú:jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú iyẹ̀wù rẹ̀.Kí ìyàwó sì kúrò nínù ìyàrá rẹ̀

17. Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa,sọkún láàrin ìlorò àti pẹpẹ,sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọnènìyàn rẹ sí Olúwa,má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn,ti àwọn aláìkọlà yóò fi má jọba lórí wọn:èéṣe tí wọn yóò fi wí láàárin àwọn ènìyàn pé,‘Ọlọ́run wọn há da?’ ”

18. Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀,yóò sì káànú fún ènìyàn rẹ̀.

19. Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn:“Yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé,Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun,àti òróró síi yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn:èmi kì yóò si fí yín ṣe ẹ̀gan mọ́ láàrin àwọn aláìkọlà.

20. “Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín,èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro,pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí òkun ìlà oòrùn,àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀ oòrùn òkun.Oòrùn rẹ̀ yóò sì gòkè,òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.”Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.

21. Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀;jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀,nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá,

22. Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó,nítorí pápá-oko ihà ń rú,nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́àti àjàrà ń so èso ipá wọn.

23. Ǹjẹ́ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Ṣíónì,ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín,nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́,Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín,àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.

24. Àwọn ilẹ̀ ìpàkà yóò kún fún ọkà;àti ọpọ́n wọn nì yóò ṣàn jádepẹ̀lú ọti wáìnì tuntun àti òróró.

25. “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín.Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewéọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòro ajẹnirun mìíràn ti fi jẹàwọn ogun ńlá mí tí mo rán sí àárin yín.

26. Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, titi ẹyin yóò fi yóẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín,ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò;ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.

27. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrin Ísírẹ́lì,àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín,ati pé kò sí ẹlòmíràn:ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.

Ọjọ́ Olúwa

28. “Yóò sì ṣe,èmi yóò tú ẹ̀mi mí sí ara ènìyàn gbogbo;àti àwọn ọmọ yín ọkùnrin,àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa ṣọtẹ́lẹ̀,àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá,àwọn ọ̀dọ́mọ́kunrìn yín yóò máa ríran.

29. Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin,àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin,ní èmi yóò tú ẹ̀mi mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.

30. Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrunàti ní àyé,ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.

31. A á sọ oòrùn di òkùnkùn,àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀ru Olúwa tó dé.

32. Yóò sí ṣe ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pèorúkọ Olúwa ní a ó gbàlà:nítorí ní òkè Ṣíónì àti ní Jérúsálẹ́mùní ìgbàlà yóò gbé wà,bí Olúwa ti wí,àti nínú àwọnìyókù tí Olúwa yóò pè.