orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42
  43. 43
  44. 44
  45. 45
  46. 46
  47. 47
  48. 48

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Àsọtẹ́lẹ̀ Édómù

1. Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:

2. “Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Séírì; ṣọtẹ́lẹ̀ síi

3. Kí o sì sọ wí pé: ‘Èyí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Séírì, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí o di ahoro.

4. Èmì yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.

5. “ ‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Ísírẹ́lì lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,

6. nítorí náà bi mo ti wà láàyè, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ̀n ìgbà tí ìwọ kò ti korìíra ìtàjẹ̀-sílẹ̀, ìtàjẹ̀-sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.

7. Èmi yóò mú kí òkè Séírì di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ńlọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.

8. Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ: àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárin àwọn òkè rẹ.

9. Èmi yóò mú kí o di ahoro títí láé; Kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.

10. “ ‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀ èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi Olúwa wà níbẹ̀,

11. nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láàyè, ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárin wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.

12. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi Olúwa ti gbọ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Ísírẹ́lì náà. Ìwọ wí pé, “A ti fi wọ́n sílẹ̀ ní ṣíṣọ̀fọ̀, a sì fi fún wa láti pajẹ.”

13. Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.

14. Èyí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro

15. Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Ísírẹ́lì di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Séírì, ìwọ àti gbogbo ará Édómù. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa.’ ”