orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 2 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Síónìpẹ̀lú ìkúùkù ìbínú rẹ̀!Ó sọ ògo Ísírẹ́lì kalẹ̀Láti ọ̀run sí ayé;kò rántí àpótí-ìtìṣẹ̀ rẹ̀ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.

2. Làìní àánú ni Olúwa gbéibùgbé Jákọ́bù mì;nínú ìrunú rẹ̀ ni ó wóibi gíga ọmọbìnrin Júdà lulẹ̀.Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ aládé ọkùnrinlọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.

3. Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó kégbogbo ìwo Ísírẹ́lì.Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrònígbà tí àwọn ọ̀tá dé.Ó run ní Jákọ́bù bí ọ̀wọ́ inání àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Síónì.

4. Ó na ọfà rẹ̀ bí ọtá;ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múraBí ti ọ̀ta tí ó ti parunó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí inásórí àgọ́ ọmọbìnrin Síónì.

5. Olúwa dà bí ọ̀tá;ó gbé Ísírẹ́lì mì.Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mìó pa ibi gíga rẹ̀ run.Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀fún àwọn ọmọbìnrin Júdà.

6. Ó mú ìparun bá ibimímọ́,ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run. Olúwa ti mú Síónì gbàgbéọjọ́ àṣè àti ọ̀ṣẹ̀ tí ó yàn;nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó runọba àti olórí àlùfáà.

7. Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.Ó sì fi lé ọ̀ta lọ́wọ́àwọn odi ààfin rẹ̀;wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwagẹ́gẹ́ bí ọjọ́ ìpèjẹ tí a yàn.

8. Olúwa pinnu láti faògiri tí ó yí ọmọbìnrin Síónì ya.Ó gbé wọn sórí òṣùnwọ̀n,kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.Ó mú kí ilé-ìsọ́ àti odi rẹ̀ sọ̀fọ̀wọ́n ṣòfò papọ̀.

9. Ẹnu ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrin àwọn orílẹ̀ èdè,kò sí òfin mọ́,àwọn wòlíì rẹ̀ kò ríìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.

10. Àwọn àgbààgbà ọmọbìnrin Síónìjókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;wọ́n da eruku sí orí wọnwọ́n sì wọ aṣọ àkísà.Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jérúsálẹ́mùti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.

11. Ojú mi kọ̀ láti sunkún,mo ń jẹ ìrora nínú mi,mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kúní òpópó ìlú.

12. Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,“Níbo ni àkàrà àti wáìnì wà?” Wò óbí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣení àwọn òpópónà ìlú,bí ayé wọn ṣe ń ṣòfòláti ọwọ́ ìyá wọn.

13. Kí ni mo le sọ fún ọ?Pẹ̀lú u kí ni mo lè fi ọ́ wé,Ìwọ ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù?Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé,kí n lè tù ọ́ nínú,Ìwọ wúndíá bìnrin Síónì?Ọgbẹ́ rẹ jìn bí òkun.Ta ni yóò wò ọ́ sàn?

14. Ìran àwọn wòlíì rẹjẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n;wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàntí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ.Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọjẹ́ èké àti ìsìnà.

15. Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹpàtẹ́wọ́ lé ọ lórí;wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọnsí ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù:“Èyí ha ni ìlú tí à ń pè níàṣepé ẹwà,ìdùnnú gbogbo ayé?”

16. Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọngbòòrò sí ọ;wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payín kekewọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán.Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí;tí a sì wá láti rí.”

17. Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu;ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ,tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́.Ó ti sí ọ nípò láì láàánú,ó fún ọ̀tá ní ìsẹ́gun lórí rẹ,ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.

18. Ọkàn àwọn ènìyànkígbe jáde sí Olúwa.Odi ọmọbìnrin Síónì,jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ ṣàn bí odòní ọ̀sán àti òru;má ṣe fi ara rẹ fún ìtura,ojú rẹ fún ìsinmi.

19. Dìde, kígbe sókè ní àsálẹ́,bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀tú ọkàn rẹ̀ jáde bí ominíwájú Olúwa.Gbé ọwọ́ yín sókè sí inítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀tí ó ń kú lọ nítorí ebiní gbogbo oríta òpópó.

20. “Wòó, Olúwa, kí o sì rò ó:Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyíǸjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn,àwọn ọmọ tí wọn ń se ìtọ́jú fún?Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíìní ibi mímọ́ Olúwa?

21. “Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀sínú eruku àwọn òpópó;àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin miti ṣègbé nípa idà.Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ;Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.

22. “Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àṣè,bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi.Ní ọjọ́ ìbínú Olúwakòsí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè;àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn,ni ọ̀ta mi parun.”