orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njúpẹ̀lú ọ̀pá ìbínú.

2. Ó ti lémi jáde ó sì mú mi rìnnínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀;

3. Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ padà sí misíwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.

4. Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran ara mi gbóó sì tún ṣẹ́ egungun mi.

5. Ó ti fi mí sí ìgbèkùn ó sì ti yí mi kápẹ̀lú ìkorò àti làálàá.

6. Ó mú mi gbé nínú òkùnkùnbí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.

7. Ó ti tì mí mọ́lé nítorí náà n kò le è sálọ;ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀

8. Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,ó kọ àdúrà mi.

9. Ó fi búlọ́kù òkúta dí ọ̀nà mi;ó sì mú ọ̀nà mi wọ́

10. Bí i béárì tí ó dùbúlẹ̀,bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.

11. Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ó fi mi sílẹ̀ láì sí ìrànlọ́wọ́.

12. Ó fa ọfà rẹ̀ yọó sì fi mí sohun ìtafàsí.

13. Ó fa ọkàn mí yapẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.

14. Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrin àwọn ènìyàn mi;wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.

15. Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkoròàti ìdààmú bí omi.

16. Ó ti fi òkúta kán ẹyín mi;ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.

17. Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;Mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.

18. Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọàti ìrètí mi nínú Olúwa.”

19. Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,ìkorò àti ìbànújẹ́.

20. Mo ṣèrántí wọn,ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.

21. Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkànàti nítorí náà ní mo nírètí.

22. Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,nítorí àánú rẹ kì í kùnà.

23. Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;títóbi ni òdodo rẹ̀.

24. Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́

25. Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,sí àwọn tí ó ń wá a.

26. Ó dára kí a ní ṣùúrùfún ìgbàlà Olúwa.

27. Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgànígbà tí ó wà ní èwe.

28. Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́jẹ́,nítorí Olúwa ti fi fún un.

29. Jẹ́ kí ó bò ojú rẹ̀ sínú eruku—ìrètí sì lè wà.

30. Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a,sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.

31. Ènìyàn kò di ìtanùlọ́dọ̀ Olúwa títí láé.

32. Lóòtọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn,nítorí náà títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.

33. Nítorí kò mọ̀ọ́mọ̀ mú ìpọ́njú wátàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.

34. Kí ó tẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.

35. Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀níwájú ẹni ńlá.

36. Láti yí ìdájọ́ ènìyàn po,Ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.

37. Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀tí Olúwa kò bá fàṣẹ sí i.

38. Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu ẹni ńláni dídára àti búburú tí ń wá?

39. Kí ló dé tí ẹ̀dá alàyè ṣe ń kùnnígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

40. Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa kí a sì dán an wò,kí a sì tọ Olúwa lọ.

41. Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókèsí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé:

42. Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jìn wá.

43. “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;ìwọ ń parun láì sí àánú.

44. Ìwọ ti fi ìkuukù bo ara rẹpé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.

45. Ó ti sọ wá di èérí àti ààtànláàrin orílẹ̀ èdè gbogbo.

46. “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọngbòòrò sí wa.

47. Àwa ti jìyà àti ìparun,nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”

48. Omijé ń ṣàn ní ojú mi bí odònítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.

49. Ojú mi kò dá fún omijé,láì sinmi,

50. títí ìgbà tí Olúwa síjú wolẹ̀láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.

51. Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn minítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.

52. Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìídẹ mí bí ẹyẹ.

53. Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihòwọ́n sì ju òkúta lù mí.

54. Orí mi kún fún omi,mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.

55. Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa,láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.

56. Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi: “Má ṣe di etí rẹsí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”

57. O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́,o sì wí pé, “Má se bẹ̀rù.”

58. Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò,o ra ẹ̀mí mi padà.

59. O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí miGbé ẹjọ́ mi ró!

60. Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn,gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.

61. Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọnàti ìmọ̀ búburú wọn sí mi—

62. Ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọsí mi ní gbogbo ọjọ́.

63. Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde,wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.

64. Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọnfún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.

65. Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn,kí o sì fi wọ́n ré.

66. Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú,lábẹ́ ọ̀run Olúwa.