orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 1 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ẹ̀kọ́ Dáníẹ́lì Ní Bábílónì.

1. Ní ọdún kẹta tí Jéhóíákímù jẹ ọba Júdà, Nebukadinéṣárì ọba Bábílónì wá sí Jérúsálẹ́mù, ó sì kọ lù ú pẹ̀lú àwọn ọmọ ogun rẹ̀.

2. Olúwa sì fa Jéhóíákímù ọba Júdà lé e lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó lọ sí ilé òrìṣà ní Bábílónì, sí inú ilé ìṣúra òrìṣà a rẹ̀.

3. Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Áṣípénásì, olórí àwọn ìwẹ̀fà ààfin rẹ̀ pé, kí ó mú nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí wọ́n wá láti ìdílé ọba àti lára àwọn tí ó wá láti ilé ọlá.

4. Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí kò ní àbùkù ara, tí wọ́n rẹwà, tí wọ́n sì fi ìfẹ́ sí ẹ̀kọ́ hàn, tí wọ́n sì ní ìmọ̀, tí òye tètè ń yé àti àwọn tí ó kún ojú òṣùwọ̀n láti ṣiṣẹ́ ní ààfin ọba kí ó kọ́ wọ́n ní èdè àti onírúurú ẹ̀kọ́ ìwé ti àwọn Bábílónì.

5. Ọba pèsè oúnjẹ ojoojúmọ́ àti wáìnì láti orí tábìlì i rẹ̀ fún wọn, ó sì kọ́ wọn fún ọdún mẹ́ta. Lẹ́yìn náà ni wọn yóò bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ fún ọba.

6. Lára àwọn wọ̀nyí ni àwọn tó wá láti Júdà: Dáníẹ́lì, Hananíáyà, Mísáẹ́lì àti Ásáríyà.

7. Olórí àwọn ìwẹ̀fà fún wọn ní orúkọ tuntun: Ó fún Dáníẹ́lì ní Beliteṣáṣárì, ó fún Hananíáyà ní Sádírákì, ó fún Mísáẹ́lì ní Mésákì àti Áṣáríyà ní Àbẹ́dinígò.

8. Ṣùgbọ́n Dáníẹ́lì pinnu ní ọkàn ara rẹ̀ pé òun kò ní ba ara òun jẹ́ pẹ̀lú oúnjẹ àti wáìnì ọba, nígbà náà ni ó gba ààyè lọ́wọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà wí pé òun kò fẹ́ ba ara òun jẹ́ ní ọ̀nà yìí.

9. Ọlọ́run mú kí Dáníẹ́lì rí ojúrere àti àánú gbà láti ọwọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà,

10. Ṣùgbọ́n olórí àwọn ìwẹ̀fà sọ fún Dáníẹ́lì pé, “Mo bẹ̀rù Olúwa mi, ẹni tí o ti pèṣè oúnjẹ àti ohun mímu rẹ. Báwo ni ìrísí ì rẹ yóò ṣe burú jù ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ẹlẹgbẹ́ ẹ̀ rẹ lọ? Nígbà náà ni èmi yóò fi orí mi wéwu lọ́dọ̀ ọba.”

11. Nígbà náà ni Dáníẹ́lì sọ fún olùṣọ́ tí olórí àwọn ìwẹ̀fà yàn lórí i Dáníẹ́lì, Hananiáyà, Mísáẹ́lì àti Ásáríyà pé,

12. Jọ̀wọ́ dán àwa ìránṣẹ́ rẹ wò fún ọjọ́ mẹ́wàá: Má ṣe fún wa ní ohun kankan, àfi ẹ̀fọ́ láti jẹ àti omi láti mu.

13. Nígbà náà ni kí o fi ìrísí i wa wé ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba, kí o sì ṣe àwa ìránṣẹ́ rẹ ní ìbámu pẹ̀lú u bí o bá ṣe rí i sí.

14. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì gbà láti dán wọn wò fún ọjọ́ mẹ́wàá.

15. Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwàá ara wọn le, wọ́n sì sanra ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba lọ.

16. Bẹ́ẹ̀ ni olùṣọ́ mú oúnjẹ àdídùn àti wáìnì tí ó yẹ kí wọ́n mu kúrò, ó sì fún wọn ní ẹ̀fọ́ dípò rẹ̀.

17. Ọlọ́run fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ní ìmọ̀ àti òyé nínú un gbogbo onírúurú ìwé àti ẹ̀kọ́ ọ wọn: Dáníẹ́lì sì ní òyé ìran àti àlá ní oríṣìíríṣìí.

18. Ní òpín ìgbà tí ọba dá, pé kí a mú wọn wá sínú ààfin, olórí àwọn ìwẹ̀fà mú wọn wá ṣíwájú ọba Nebukadinésárì.

19. Ọba sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì rí i pé kò sí ẹni tí ó dàbí i Dáníẹ́lì, Hananíáyà, Míṣáẹ́lì àti Ásáríyà; Nítorí náà wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe iṣẹ́ ọba.

20. Nínú un gbogbo ọ̀ràn, ọgbọ́n àti òyé tí ọba ń bèrè lọ́wọ́ ọ wọn, ó rí i pé wọ́n sàn ní ìlọ́po mẹ́wàá ju gbogbo àwọn amòye àti ọlọ́gbọn tí ó wà ní gbogbo ìjọba rẹ̀.

21. Dáníẹ́lì sì wà níbẹ̀ títí di ọdún kìn-ín-ní ọba Kírúsì.