orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42
  43. 43
  44. 44
  45. 45
  46. 46
  47. 47
  48. 48
  49. 49
  50. 50
  51. 51
  52. 52

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 51 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ohùn ti Olúwa nìyìí:“wò ó èmi yóò ru ẹ̀míapanirun kan sókè síBábílónì àwọn ènìyàn Lébíkámáì

2. Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn síBábílónì láti ba ilẹ̀ jẹ́,wọn yóò ṣe àtakò rẹ̀ ní gbogboọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.

3. Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀jáde tàbí kí o di ìhámọ́ra rẹ̀;má ṣe dá àwọn ọdọ́mọkùnrinsí, pátapáta ni kí o pa àwọn ọmọ ogun rẹ̀.

4. Gbogbo wọn ni yóò ṣubúní Bábílónì tí wọn yóò sìfarapa yánna yànna ní òpópónà.

5. Nítorí pé Júdà àti Ísírẹ́lì niỌlọ́run wọn tí í se Olúwa alágbárakò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọnkún fún kìki ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì.

6. “Sá kúrò ní Bábílónì! Sá àsálàfún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.Àsìkò àti gbẹ̀san Ọlọ́run ni èyí,yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.

7. Ifẹ́ wúrà ni Bábílónì ní ọwọ́ Olúwa;ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí.Gbogbo orílẹ̀ èdè mu ọtí rẹ̀,wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.

8. Bábílónì yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́;sunkún fún un! Wá báàmù fún ìrora rẹ,bóyá yóò le wo ọ́ sàn.

9. “ ‘À bá ti wo Bábílónì sàn,ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀,kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè,ó ga àní títí dé òfurufù.’

10. “ ‘Olúwa ti dá wa láre,wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Síónì ohun tí OlúwaỌlọ́run wa ti ṣe.’

11. “Lọ ọfà wa kó mú, mú apata! Olúwa ti ru Ọba Médíà sókè,nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Bábílónì run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún Tẹ́ḿpìlì rẹ̀.

12. Gbé àsìá sókè sí odi Bábílónì!Ẹ ṣe àwọn ọmọ ogun gírí,ẹ pín àwọn olùsọ́ káàkiri,ẹ ṣètò àwọn tí yóò sápamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde,òfin rẹ̀ sí àwọn ará Bábílónì.

13. Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀,tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé,àní àsìkò láti ké ọ kúrò!

14. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀,Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú,wọn yóò yọ ayọ̀, iṣẹ́gun lórí rẹ.

15. “Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀,o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.

16. Nígbà tí ará omi ọ̀run hóó mú kí òfùrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé.Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.

17. “Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọtí kò sì ní ìmọ̀, olúkùlúkùalágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀.Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn wọn kò ní èémí nínú.

18. Wọn kò já mọ́ nkànkan,wọ́n jẹ́ ohun ẹlẹ́yà nígbà tí ìdájọ́ wọnbá dé, wọn ó ṣègbé.

19. Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jákọ́bù kó rí bí ìwọ̀nyí;nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo,àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa alágbára ni orúkọ rẹ̀.

20. “Ìwọ ni kùmọ̀ ohun èlò ogun mi,ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀ èdè túútúú,èmi ó bà àwọn ilé Ọba jẹ́.

21. Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀;èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lúèmi ó pa awakọ̀

22. Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin,pẹ̀lú rẹ, mo paàgbàlagbà àti ọmọdé,Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.

23. Pẹ̀lú rẹ, mo pa olùsọ́ àgùntànàti agbo àgùntàn rẹ̀;pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbẹ̀ àti màlúù,Pẹ̀lú rẹ, mo pa gómìnà àti àwọn alákòóṣo ìjọba rẹ̀.

24. “Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Bábílónì àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Síónì,”ni Olúwa wí.

25. “Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirunìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,”ni Olúwa wí.“Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ,èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta,Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.

26. A kò ní mú òkúta kankan látiọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbífún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò diahoro títí ayé,”ní Olúwa wí.

27. “Gbé àṣíá sókè ní ilẹ̀ náà, fọnipe láàrin àwọn orílẹ̀ èdè!Pèṣè àwọn orílẹ̀ èdè sílẹ̀ láti bá jagun,pe àwọn ìjọba yìí láti doju kọ ọ́,Árárátì, Mínínì àti Ásíkẹ́nì.Yan olùdarí ogun láti kọlù ú,rán àwọn ẹṣin síi bí ọ̀pọ̀ eṣú.

28. Pèsè àwọn orílẹ̀ èdè láti bá jagun,àwọn Ọba Médíà, Gómìnà àti gbogboọmọ ìgbìmọ̀ wọn àti gbogbo orílẹ̀ èdè tí wọ́n jọba lé lórí.

29. Ilẹ̀ wárìrì síhìn ín sọ́hùn ún, nítorí péète Olúwa, sí Bábílónì dúróláti ba ilẹ̀ Bábílónì jẹ́ lọ́nàtí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.

30. Gbogbo àwọn jagunjagunBábílónì tó dáwọ́ ìjà dúró la sí àgọ́ wọn.Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin.Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun,gbogbo irin ẹnu ọ̀nà wọn ti di fífọ́.

31. Iránsẹ́ kan ń tẹ̀lé òmírànláti sọ fún Ọba Bábílónì pégbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.

32. Odò tí ó ṣàn kọjá kò ṣàn mọ́ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”

33. Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ nìyìí:“Ọmọbìnrin Bábílónì dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”

34. “Nebukadinésárì Ọba Bábílónì tó jẹ wá run,ó ti mú kí ìdààmú bá wa,ó ti sọ wá di àgbá òfìfo.Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì.Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀,lẹ́yìn náà ni “Ó pọ̀ wá jáde.

35. Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe síẹran ara wa wà lórí Bábílónì;”èyí tí àwọn ibùgbé Síónì wí.“Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogboàwọn tí ń gbé Bábílónì,”ni Jérúsálẹ́mù wí.

36. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí:“Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lóríohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san,èmi yóò mú kí omi òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.

37. Bábílónì yóò parun pátapáta,yóò sì di àwọn akáta,ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.

38. Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramùbí ọmọ kìnìún.

39. Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè,èmi yóò se àsè fún wọn,èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó débití wọn yóò máa kọ ẹ̀rín lẹ́yìn náà,wọn yóò sun oorun àsùnjí,”ni Olúwa wí.

40. “Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.

41. “Bí Sésákì yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé.Irú ìpàyà wo ni yóò báBábílónì láàrin àwọn orílẹ̀ èdè!

42. Òkun yóò ru borí Bábílónì,gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Bábílónì.

43. Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro,ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ tí ènìyànkò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.

44. Èmi yóò fi ìyà jẹ Bélì tiBábílónì àti pé èmi yóòjẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì.Orílẹ̀ èdè kò ní i jẹ́ ìṣàn fún-un mọ́.Odi Bábílónì yóò sì wó.

45. “Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ẹ̀yin ènìyàn mi!Sá àṣálà fún ẹ̀mi rẹ!Sá fún ìbínú ńlá Ọlọ́run.

46. Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrútàbí kí o bẹ̀rù nígbà tía bá gbọ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa;àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí,òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipání ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.

47. Nítorí ìgbà náà yóò wádandan nígbà tí èmiyóò fi ìyà jẹ àwọnòrìṣà Bábílónì, gbogbo ilẹ rẹ̀ ni a ó dójú tìgbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárin rẹ̀.

48. Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn,yóò sì kọrin lórí Bábílónì:nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,”ni Olúwa wí.

49. “Gẹ́gẹ́ bí Bábílónì ti mú kí àwọn olùpa Ísírẹ́lì ṣubúbẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní àwọn olùpa gbogbo ilẹ̀ ayé yóò ṣubú.

50. Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró:Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè,ẹ sì jẹ́ kí Jérúsálẹ́mù wá sí ọkàn yín.”

51. “Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn:ìtìjú ti bò wá lójúnítorí àwọn àlejò wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”

52. “Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí,“tí èmi yóò se ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fífin rẹ̀:àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa gbin já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀

53. Bí Bábílónì tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run,bí ó sì ṣe ìlú olodi ní òkè agbára rẹ,síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,”ní Olúwa wí.

54. “Ìró igbe láti Bábílónì,àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kálídéà!

55. Nítorí pé Olúwa ti ṣe Bábílónì ní ìjẹ,ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀;rírú wọn sì ń hó bi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.

56. Nítorí pé afiniṣe ìjẹ dé sórí rẹ̀,àní sórí Bábílónì;a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn:nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa,yóò san án nítòótọ́.

57. Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí,àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀àti àwọn alákòóṣo rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀,wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,”ní Ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa ọmọ ogun.

58. Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ ogun wí:“Odi Bábílónì gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátapáta,ẹnu bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun:tóbẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán,àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná,tí àárẹ̀ sì mú wọn.”

59. Ọ̀rọ̀ tí Jeremáyà wòlíì pàṣẹ fún Seráíyà, ọmọ Néríà, ọmọ Mááséíyà, nígbà tí o ń lọ ni ti Ṣedekáyà, Ọba Júdà, sí Bábílónì ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Séráíà yí sì ní ìjòyè ibùdó.

60. Jeremáyà sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Bébálì sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ wọ̀nyí tí a kọ sí Bábílónì.

61. Jeremáyà sì sọ fún Séráíà pé, “nígbà tí ìwọ bá dé Bábílónì, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.

62. Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’

63. Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárin odò Éfúrétè:

64. Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Bábílónì yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’ ”Títí dé ìhín nií ọ̀rọ̀ Jeremáyà.