orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sekaráyà 13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ìwẹ̀nùmọ́ Kúrò Nínú Ẹ̀ṣẹ̀

1. “Ní ọjọ́ náà isun kan yóò sí sílẹ̀ fún ilé Dáfídì àti fún àwọn ará Jérúsálẹ́mù, láti wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìmọ́ wọn.

2. “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ni èmi ó gé orúkọ àwọn òrìṣà kúrò ni ilẹ̀ náà, a kì yóò sì rántí wọn mọ́: àti pẹ̀lú èmi ó mú àwọn wòlíì èké àti àwọn ẹ̀mí àìmọ́ kọjá kúrò ni ilẹ̀ náà.

3. Yóò sì ṣe, nígbà tí ẹnìkan yóò ṣọtẹ́lẹ̀ ṣíbẹ̀, ni baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí ó bí í yóò wí fún un pé, ‘Ìwọ ki yóò yè: nítorí ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ èké ni orúkọ Olúwa.’ Àti baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí o bí í yóò gun un ni àgúnpa nígbà tí ó bá ṣọtẹ́lẹ̀.

4. “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ojú yóò tí àwọn wòlíì èké olúkúlúkù nítorí ìran rẹ̀, nígbà tí òun ba tí ṣọtẹ́lẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì wọ aṣọ wòlíì onírun rẹ̀ tí o fi ń tan ní jẹ.

5. Ṣùgbọ́n òun o wí pé, ‘Èmi kí í ṣe wòlíì, àgbẹ̀ ni èmi; nítorí tí a ti fi mí ṣe ìránṣẹ́ láti ìgbà èwe mi wá.’

6. Ẹnìkan ó sì wí fún un pé, ‘Ọgbẹ́ kín ní wọ̀nyí ni ẹ̀yìn rẹ?’ Òun o sì dáhùn pé, ‘Wọ̀nyí ni ibi tí a ti sá mi ní ilé àwọn ọ̀rẹ́ mi.’

A Lu Olùṣọ́-àgùntàn, Agbo Ẹran Fọ́nká

7. “Díde, ìwọ idà, sí olùṣọ́-àgùntàn mi,àti sí ẹni tí í ṣe ẹnìkejì mi,”ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:“Kọlu Olùṣọ́-àgùntàn,àwọn àgùntàn a sì túká:èmi o sì yí ọwọ́ mi sí àwọn kékèké.

8. Yóò sì ṣe, ni gbogbo ilẹ̀,” ni Olúwa wí,“a ó gé apá méjì nínú rẹ̀ kúrò yóò sì kú;ṣùgbọ́n apá kẹta yóò kù nínú rẹ̀.

9. Èmi ó sì mú apá kẹ́ta náà la àárin iná,èmi yóò sì yọ́ wọn bí a ti yọ́ fàdákà,èmi yóò sì dán wọn wò, bi a tí ń dán góòlu wò:wọn yóò sì pé orúkọ mi,èmi yóò sì dá wọn lóhùn:èmi yóò wí pé, ‘Àwọn ènìyàn mi ni,’àwọn yóò sì wí pé, ‘Olúwa ni Ọlọ́run wa.’ ”