Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 23:12-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Júdà ti wọ́n gbé dúró ní ori òrùlé lẹ́bá yàrá òkè ti Áhásì pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Mánásè ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó sí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kídírónì.

13. Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà oòrùn Jérúsálẹ́mù ní ìhà gúṣù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Ṣólómónì ọba Ísírẹ́lì ti kọ́ fún Ásítórétì ọlọ́run ìríra àwọn ará Ṣídónì, fún Kémóṣì ọlọ́run ìríra àwọn ará Móábù àti fún Mólékì, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ámónì.

14. Jòṣíàh fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé òpó Áṣérà lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.

15. Àní pẹpẹ tí ó wà ní Bétélì ibi gíga tí Jéróbóámù ọmọ Nébátí dá. Tí ó ti fa Ísírẹ́lì láti ṣẹ̀—Àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì ṣun òpó Áṣérà pẹ̀lú.

16. Nígbà náà, Jòṣíà wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn iṣà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.

17. Ọba sì béèrè, pé “Kí ni ọwọ́n iṣà òkú yẹn tí mo rí?”Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí iṣà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Júdà, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Bétélì, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”

18. “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Ṣamáríà.

19. Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Bétélì, Jòṣíàh sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Ísírẹ́lì ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Ṣamáríà, tí ó ti mú Olúwa bínú.

Ka pipe ipin 2 Ọba 23