Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 6:4-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Nígbà náà ni ó sì wí pé:“Ògo ni fún Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ mú ohun tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dáfídì baba mi ṣẹ. Nitorí tí ó wí pé,

5. ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì, èmi kò yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì, láti kọ́ ilé, kí orúkọ mi kí ó lè wà níbẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yan ẹnikẹ́ni láti jẹ́ olórí lórí Ísirẹ́lì ènìyàn mi.

6. Ṣùgbọ́n nísinyìí èmi ti yan Jérúsálẹ́mù, kí orukọ mi leè wà níbẹ̀, èmi sì ti yan Dáfídì láti jọba lórí Ísírẹ́lì ènìyàn mi.’

7. “Baba mi Dáfídì ti ní-in lọ́kàn láti kọ́ tẹ́ḿpìlì fún orúkọ Olúwa, àní Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

8. Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Dáfídì baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ tẹ́ḿpìlì yìí fún orúkọ mi, ìwọ ṣe ohun dáradára láti ní èyí ní ọkàn rẹ̀.

9. Ṣùgbọ́n síbẹ̀, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ tẹ́ḿpìlì náà, bí kò ṣe ọmọ rẹ, ẹni tí o jẹ́ ẹran ara àti ẹ̀jẹ̀ rẹ: òun ni yóò kọ́ tẹ́ḿpìlì fún orúkọ mi.’

10. “Olúwa sì ti mú ìléri rẹ̀ ṣẹ. Èmi ti dìde ní ipò Dáfídì baba mi, a sì gbé mi ka ìtẹ́ Ísírẹ́lì, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣe ìlérí, èmi sì ti kọ́ tẹ́ḿpìlì fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

11. Níbẹ̀ ni èmi sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí, nínú èyí ti májẹ̀mú ti Olúwa bá àwọn Ísirẹ́lì ènìyàn mi dá wà.”

12. Nígbà naà ni Sólómónì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, ní iwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Isírẹ́lì, ó sì tẹ́ ọwọ́ọ rẹ̀ méjèèjì.

13. Sólómónì ṣe àga idẹ kan tí ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn ún ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ márùn ún fífẹ̀ àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta ní gíga, a gbé e sí àárin àgbàlá ti òde. Ó sì dúró ní orí rẹ̀, àti pé ó kúnlẹ̀ lórí eékún rẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Isírẹ́lì, ó sì tẹ́ ọwọ́ọ rẹ̀ méjèèjì sí òkè ọ̀run.

14. Ó wí pé:“Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, kò sí Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ ní ọ̀run àti ní ayé: ìwọ tí o pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi tọkàntọkàn wọn rìn ní ọ̀nà rẹ.

15. Ìwọ tí o pa ìlérí tí o ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ Dáfídì baba mi mọ́; nítorí ìwọ ti fi ẹnu rẹ ṣe ìlérí àti pé ìwọ ti fi ọwọ́ rẹ mú un ṣẹ; bí ó ti rí lónìí yìí.

16. “Nísinsinyìí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, pa ìlérí tí ó ti ṣe mọ́ fún ìransẹ́ rẹ Dáfídì baba mi nígbà tí o wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ kù láti ní ọkùnrin láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Isírẹ́lì, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ tí wọ́n bá kíyèsíara nínú gbogbo ohun tí wọ́n ṣe láti rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí òfin mi gẹ́gẹ́ bí o sì ti ṣe.’

17. Nísinsìnyí, Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti sèlérí fún ìránṣẹ́ rẹ Dáfídì kí ó wá sí ìmúṣẹ.

18. “Ṣùgbọ́n ṣé Ọlọ́run nítòótọ́ yóò máa bá àwọn ènìyàn gbé lórí ilẹ̀ ayé bí? Ọ̀run, àti ọ̀run gíga kò le gbà ọ́. Báwo ni ó ṣe kéré tó, ilé Olúwa tí mo ti kọ́!,

19. Síbẹ̀ ṣe àfiyèsí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi, gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 6