orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọdún kéje, Jehóádà fi agbára rẹ̀ hàn. O dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn alákòóso, ọrọrún kan, Ásáríyà ọmọ Jérohámù, Íṣímáẹ́lì ọmọ Jehóhánániì Ásáríyà ọmọ Óbédì, Máséyà ọmọ Ádáyà àti Élíṣáfátì ọmọ Ṣkírì.

2. Wọ́n lọ sí gbogbo Júdà, wọ́n sì pe àwọn ará Léfì àti àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn ará Ísírẹ́lì láti gbogbo àwọn ìlú jọ. Nígbà tí wọ́n wá sí Jérúsálẹ́mù.

3. Gbogbo ìpéjọ dá májẹ̀mú pẹ̀lú ọba ní ilé Ọlọ́run.Jéhóiádà wí fún wọn pé, “Ọmọkùnrin ọba yóò jọba, bí Olúwa ti ṣèlérí nípa àwọn àtẹ̀lé Dáfídì.

4. Nísinsinyìí èyí ni ohun tí ó yẹ kí ó ṣe: Ìdámẹ́ta àlùfáà yín àti àwọn ará Léfì tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi ni kí ó bojútó àwọn ìlẹ̀kùn.

5. Ìdámẹ́ta yín níbi ààfin ọba àti ìdámẹ́ta níbi ẹnu odi ìdásílẹ̀ àti gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí ó wà ní àgbàlá ààfin ilé Olúwa.

6. Kò sí ẹnìkan tí ó gbọdọ̀ wọ inú ilé Olúwa yàtọ̀ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Léfì tí a rán ní iṣẹ́ ìsìn. Wọ́n lè wọlé nítori tí a ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ṣùgbọ́n gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí wọn ó ṣọ ohun tí Olúwa ti yàn fún wọn.

7. Àwọn ará Léfì gbọ́dọ̀ wà ní ìdúróṣinṣin yí ọba ká. Olúkúlùkù pẹ̀lú àwọn nǹkan ìjà ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ ilé Olúwa ni kí ẹ pa. Ẹ dúró ti ọba níbikíbi tí ó bá lọ.”

8. Àwọn ará Léfì àti gbogbo ọkùnrin Júdà ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehóádà Àlùfáà ti palásẹ. Olukúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀, àwọn tí wọ́n lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n ń kúrò ní ibi iṣẹ́. Nítorí Jéhóiádà àlùfáà kò ì tí tú ìpín kankan sílẹ̀.

9. Nígbà náà, ó fún àwọn alákòóso ọrọrún ní ọkọ̀ àti ńlá àti kékeré apata, tí ó jẹ́ ti ọba Dáfídì tí wọn wà ní ilé Ọlọ́run.

10. Ó mú gbogbo àwọn ọkùnrin wà ní ipò ìdúró pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, yí ọba ká ní ẹ̀bá pẹpẹ àti ilé Olúwa láti ìhà gúsù sí ìhà àríwa ilé Olúwa.

11. Jéhóiádà àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mú ọmọkùnrin ọba jáde wá wọ́n sì gbé adé sórí rẹ̀; Wọ́n mú ẹ̀dà májẹ̀mú kan fún un. Wọ́n sì kéde rẹ̀ lọ́ba. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, wọ́n sì kígbe pé, “Kí ọba kí ó pẹ́!”

12. Nígbà tí Ataláyà gbọ́ igbe àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sáré tí wọ́n ń kígbe ọba, ó lọ sí ọ̀dọ̀ wọn ní ilé Olúwa.

13. Ó sì wò, sì kíyèsì, ọba dúró ní ibùdúró rẹ̀ ní ẹ̀bá ẹnu-ọ̀nà, àti àwọn balógun àti àwọn afọ̀npè lọ́dọ̀ ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, wọ́n sì fọn ìpè, àti àwọn akọrin pẹ̀lú ohun èlò ìyìn, Nígbà náà ni Ataláyà fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì kégbe wí pé, “ọ̀tẹ̀! ọ̀tẹ̀!”

14. Jéhóiádà àlùfáà mú àwọn alákóso ọrọrún, tí ó wà ní àbojútó àwọn ọ̀wọ́ ogun, ó sì wá wí fún wọn pé: “Mú un jáde wá láàrin àwọn ọgbà, kí ẹ sì pa ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀le.” Nítorí tí àlùfáà ti wí pé, “Má se paá nínú ilé Olúwa.”

15. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi ipá mú un kí ó tó dé ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti ẹnu-òde ẹsin ní ìpìlẹ̀ ààfin. Níbẹ̀ ni wọ́n sì ti pa á.

16. Jéhóiádà, nígbà náà dá májẹ̀mú pé òun àti àwọn ènìyàn àti ọba yóò jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run.

17. Gbogbo Àwọn ènìyàn lọ sí ilé Báálì, wọ́n sì fà á ya lulẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti àwọn òrìṣà, wọ́n sì pa Mátanì àlùfaà Báálì níwáju àwọn pẹpẹ.

18. Nígbà náà, Jéhóiádà tẹ àwòrán ilé Olúwa sí ọwọ́ àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ará Leì ẹni tí Dáfídì ti fi ṣe iṣẹ́ ní ilé Olúwa láti tẹ ọrẹ sísun ti Olúwa bí a ti kọ ọ́ nínú òfin Mósè. Pẹ̀lú ayọ̀ Àti orin kíkọ, gẹ́gẹ́ bí Dáfídì ti pàsẹ.

19. Ó mú àwọn olùsọ́nà wà ni ipò ìdúró ní ẹnu odi ilé Olúwa kí ẹni aláìmọ́ nínú ohun-kóhun kó má baà wọlé.

20. Ó mú pẹ̀lú rẹ̀ àwọn alákóso ọrọrún, Àwọn eni-ọlá, àwọn olórí àwọn ènìyàn àti gbogbo àwọn Ènìyàn ilẹ̀ náà. Ó sì mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé Olúwa. Wọ́n lọ sínú Ààfin láti ẹnu òde tòkè. Wọ́n sì fi ọba jókoó lórí ìtẹ́.

21. Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì ń yọ̀. Ìlú naà sì dákẹ́ rọ́rọ́. Nítorí tí a pa Ataláyà pẹ̀lú idà.