orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Mikáyà Sọtẹ́lẹ̀ Lórí Áhábù

1. Nísinsin yìí Jéhóṣáfátì sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Áhábù nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.

2. Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Áhábù lálejò ní Saaríà. Áhábù sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramótì Gílíádì.

3. Áhábù ọba Ísírẹ́lì sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jèhóṣáfátì, ọba Júdà pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Rámótì Gílíádì?”Jehóṣáfátì sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ ninú ogun naà”

4. Ṣùgbọ́n Jehóṣáfátì náà sì tún wí fún ọba Ísírẹ́lì pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”

5. Bẹ́ẹ̀ ọba Ísírẹ́lì kó àwọn wòlíì papọ̀, irínwó (4,000) ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Rámótì Gélíádì tàbi kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?”“Lọ,” wọ́n dáhùn, “nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”

6. Ṣùgbọ́n Jehósáfátì béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”

7. Ọba Ìsírélì dá Jehóṣáfatì lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ì bá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorì kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Míkáyà ọmọ Ímílà.”“Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀,” Jehóṣáfátì sì dá lóhùn.

8. Bẹ́ẹ̀ ni ọba Ísírẹ́lì pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹmú Míkáyà ọmọ Ímílà kí ó yára wá.”

9. Wọ́n wọ aṣọ Ìgúnwà wọn, ọba Ísírẹ́lì àti Jehóṣáfátì ọba Júdà wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu bodè Samaríà, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.

10. Nísinsin yìí Sedekáyà ọmọ Kénánà sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Síríà títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.”

11. Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ̀lẹ́ ní àkókò kan náà, “Wọ́n sì wí pé, dojúkọ Rámótì Gílíádì ìwọ yóò sì ṣẹ́gun,” wọ́n wí pé, “nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”

12. Ìránsẹ́ tí ó ti lọ pe Míkáyà sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó níí ṣe pẹ̀lú ti wa, kí o sì sọ rere.”

13. Ṣùgbọ́n Míkáyà wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láàyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”

14. Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Míkáyà, se kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Rámótì Gílíádì, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?”“Ẹ dojú kọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun.” Ó dahùn, “nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”

15. Ọba sì wí fún-un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”

16. Nígbà náà Míkáyà dáhùn, “Mo rí gbogbo Ísírẹ́lì fọ́n káàkiri lórí àwọn òkè, bí àgùntàn tí kò ní olùsọ́. Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò ní ọ̀gá. Jẹ́ kí olúkúlùkù lọ sí ilé ní àlàáfíà.’ ”

17. Ọba Ísírẹ́lì wí fún Jéhóṣáfátì pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”

18. Mikáyà tẹ̀ṣíwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa: Mo rí Olúwa jòkó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.

19. Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Áhábù ọba Ísírẹ́lì lọ sí Rámátì Giléádì kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’“Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.

20. Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá ṣíwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’“ ‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa beèrè.

21. “ ‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ Ó wí pé.“ ‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’

22. “Bẹ́ẹ̀ ni nísinsìn yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”

23. Nígbà náà Sedékíà ọmọ Kénánà lọ sókè ó sì gbá Míkáyà ní ojú. “Ní ọ̀nà wo níi ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?” Ó sì bèèrè.

24. Míkáyà sì dáhùn pé, “ìwọ yóò ṣe ìwadìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sápamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”

25. Ọba Ísírẹ́lì paálásẹ pé, “Mú Mikáyà kí o sì ran padà sí Ámónì olóri ìlú àti sí Jóáṣì ọmọ ọba,

26. Ó sì wí pé ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ: ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún-un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’ ”

27. Míkáyà sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún-un pé, “Ẹgbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”

A Pa Áhábù Ní Rámótì Gílíádì

28. Bẹ́ẹ̀ ni ọba Ísírẹ́lì àti Jéhóṣáfátì ọba Júdà lọ sókè ní Rámótì Gílíádì.

29. Ọba Ísírẹ́lì sọ fún Jéhóṣáfátì pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgunwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Ísírẹ́lì pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.

30. Nísinsìn yìí ọba Síríà ti pàsẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Ísírẹ́lì.”

31. Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jéhóṣáfátì, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Ísírẹ́lì.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jéhóṣáfátì kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,

32. Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ ríi wí pé kì í ṣe ọba Ísírẹ́lì, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.

33. Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Ísírẹ́lì láàárin ìpàdé ẹ̀wù ìrin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”

34. Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ síi, ọba Ísírẹ́lì dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Síríà títí ó fi di àsaálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.