orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ìkìlọ Láti Inú Ìtàn Àwọn Ọmọ Ísírẹ́lì

1. Nítorí èmi kò fẹ́ kí ẹ̀yin jẹ́ òpè si òtítọ́, ẹ̀yin arakùnrin ọ̀wọ́n, a kó gbọdọ̀ gbàgbé ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn wa nínú ihà. Ọlọ́run samọ̀nà wọn nípa rírán ìkùúkù ṣíwájú wọn, ó sì sìn wọ́n la omi òkun pupa já.

2. A lè pe eléyìí ní ìtèbọmi sí Mósè nínú ìkùúkù àti nínú omi òkun.

3. Nípa iṣẹ́ ìyanu, gbogbo wọn jẹ oúnjẹ ẹ̀mí kan náà.

4. Wọ́n mu nínú omi tí Kírísítì fi fún wọn. Wọ́n mu omi ẹ̀mí láti inú àpáta tí ó ń tẹ̀lé wọn, àpáta náà ni Kírísítì. Ó wà pẹ̀lú wọn nínú ihà náà, òun ni àpáta tí ń fi omi ẹ̀mí tu ọkàn lára.

5. Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ lẹ́yin èyí, ọ̀pọ̀ nínú wọn ni kò ṣe ìgbọ́ràn sí Ọlọ́run. Òun sì pa wọ́n run nínú ihà.

6. Ẹ̀kọ́ tí a lè kọ́ yìí jásí àpẹrẹ fún wa, kí a má ṣe ní ìfẹ̀ sí àwọn ohun búburú gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn nínú ihà.

7. Kí ẹyin má ṣe sin ère òrìṣà gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Àwọn ènìyàn náà jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde dúró láti jó.”

8. Bẹ́ẹ̀ ni kí àwa kí ó má ṣe ṣe àgbérè gẹ́gẹ́ bí àwọn mìíràn nínú wọn ti ṣe, tí ẹgbàá-mọ̀kànlá-lé-ẹgbẹ̀rún ènìyàn sì kú ní ọjọ́ kan.

9. Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin má ṣe dán Olúwa wò, gẹ́gẹ́ bí àwọn mìíràn nínú wọn ti dán an wò, tí a sì fi ejò run wọ́n.

10. Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó má ṣe kùn, gẹ́gẹ́ bí àwọn mìíràn nínú wọ́n ṣe kùn, tí a sì ti ọwọ́ olùparun run wọ́n.

11. Gbogbo àwọn nǹkan tí mo ń wí wọ̀nyí ṣẹlẹ̀ sí wọn, wọ́n sì jẹ́ àpẹrẹ, fún wa, wọ́n kọ wọ́n sílẹ̀ bí ikìlọ̀ fún wa láti yàgò kúrò nínú síṣe àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀. A kọ èyí sílẹ̀ fún kíkà wa ní àkókò yìí tí aye fi ń lọ sópin.

12. Nítorí náà, ẹni tí ó bá rò pé òun dúró, kí ó kíyèsára kí ó ma ba à subú.

13. Kò sí ìdànwò kan tí ó ti bá yín, bí kò ṣe irú èyí tí ó ti bá ènìyàn rí, ṣùgbọ́n olódodo ni Ọlórun, ẹni ti kì yóò jẹ́ kí á dán an yín wò ju bí ẹ̀yin ti le gbà, ṣùgbọ̀n tí yóò sì ṣe ọ̀nà àbáyọ pẹ̀lú nínú ìdánwò náà, kí ẹ́yin baà lè faradà á.

Oúnjẹ Òrìṣà Àti Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa

14. Nítorí náà, ẹ̀yín olùfẹ́ ọ̀wọ́n, ẹ sá fún ìbọ̀rìṣà.

15. Èmi ń sọ̀rọ̀ sí ọlọ́gbọ́n ènìyàn, ṣe ìdájọ́ fúnra rẹ̀ ohun tí mo sọ.

16. Ago ìbùkún tí a ń súre sí, kì í ha ṣe jíjẹ́ alábàápín ìdàpọ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ Kírísítì bí? Àkàrà tí a bù, kì í ha ṣe jíjẹ́ alábàápín nínú ara Kírísítì bi?

17. Bí ó ti wù kí ènìyàn pọ̀ níbẹ́ tó, gbogbo wa ní ń jẹ lára àkàrà ẹyọkan ṣoṣo náà Eléyìí fi hàn wá pé gbogbo wá jẹ́ ẹ̀yà ara kan.

18. Ẹ wo Ísírẹ́lì nípa ti ara, àwọn tí ń jẹ ohun ẹbọ kò ha se alábàápín pẹpẹ bí?

19. Ǹjẹ́ kí ni mo ń wí? Ṣé pé ohun tí a fi rubọ sí òrìsà jẹ́ nǹkan kan tàbí pé òrìsà jẹ́ nǹkan kan?

20. Rárá, ṣùgbọ́n ohun tí mo ń wí ni pé, ohun tí àwọn aláìkọlà fi ń rúbọ wọn sí àwọn ẹ̀mí èsù. Dájúdájú kì í ṣe ìrúbọ sí Ọlọ́run. Èmi kò sì fẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú yín so ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ ẹ̀mí èṣù.

21. Ẹ̀yin kò lè mu nínú kọ́ọ́bù tí Olúwa àti kọ̀ọ́bù ti èṣù lẹ̀ẹ́kan náà. Ẹ kò lè jẹun ní tábìlì Olúwa kí ẹ tún jẹ tábìlì ẹ̀mí èsù lẹ́ẹ̀kan náà.

22. Kí ni ẹ̀ ń gbìyànjú láti ṣe? Àwa ha ń mú Olúwa jowú bí? Àwa ha ní agbára jù ú lọ?

Òmìnira Awọn Onígbàgbọ́

23. “Ohun gbogbo ni o yẹ fún mi,” ṣùgbọ̀n kì í ṣe ohun gbogbo ni ó ní èrè. “Ohun gbogbo ni ó yẹ fún mi,” ṣùgbọ́n kì í ṣe ohun gbogbo ni ń gbe ni rò.

24. Má ṣe ronú nípa ara rẹ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n kí olúkúkù máa wá ire ọmọnikéji rẹ̀.

25. Jẹ ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá ń tà lọ́jà. Má ṣe gbìyànjú láti wádìí lọ́wọ́ ẹni tí ń tà á nítorí ẹ̀rí ọkàn.

26. Nítorí “Ayé àti gbogbo nǹkan rere tí ń bẹ nínú rẹ̀, tí Olúwa ni wọ́n jẹ́.”

27. Bí ẹnìkẹ̀ni tí kì í bá ṣe onígbàgbọ́ ba pè yín sí ibi àṣè láti jẹun, bá a lọ. Gba ìpè rẹ̀ tí ó bá tẹ́ ọ lọ́rún. Jẹ ohunkóhun tí ó bá pèsè sílẹ̀ fún àṣè náà, má ṣe béèrè ohunkóhun nípa rẹ̀ nítorí ẹ̀rí ọkàn.

28. Bí ẹnikẹ́nì bá sì kìlọ̀ fún un yín pé a ti fi ẹran yìí rúbọ sí òriṣà, má ṣe jẹ́ ẹ nítorí ẹ̀rí ọkàn tí ó kìlọ̀ fún ọ́ pé a ti fi rúbọ sí òrìṣà.

29. Nǹkan tí ó ṣe pàtàkì ní irú ipò yìí ni ẹ̀rí ọkàn àti èrò ọkùnrin náà, nítorí kì í ṣe ẹ̀rí ọkàn ẹlòmìíràn ní a ó fi dá òmìnira mi lẹ́jọ́.

30. Bí èmi ba fi ọpẹ́ jẹ ẹ́, è é ṣe tí a fì ń sọ̀rọ̀ mi ní búbúrú nítorí ohun tí èmi dúpẹ́ fún.

31. Nítorí náà tí ẹ̀yin bá jẹ tàbí tí ẹ bá mu tàbí ohunkohun tí ẹ̀yin bá sè, e máa ṣe gbogbo rẹ̀ fún ògo Ọlọ́run.

32. Nítorí náà, má ṣe jẹ́ òkúta ìkọ̀sẹ̀ (tí ó lè gbé ẹlòmíràn subú) ìbá à ṣe Júù tàbí Gíríkì tàbí ìjọ Ọlọ́run rẹ̀.

33. Bí ṣè n gbìyanjú láti tẹ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan lọ́rùn nínú gbogbo nǹkan tí mo bá ń ṣe láì wa ohun rere fún ara mi bí kò ṣe ti ènìyàn púpọ̀ kí ó lè ṣe é ṣe fún wọn láti le ní ìgbàlà.