orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Tẹ́ Òróró Òun Àkàrà Ṣíwájú Olúwa

1. Olúwa sọ fún Mósè pé

2. “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì láti mú òróró tí ó mọ́ tí a fún láti ara ólífì wá láti fi tan iná, kí àtùpà lè máa jò láì kú.

3. Lẹ́yìn aṣọ títa tibi àpótí ẹ̀rí tí ó wà ní inú àgọ́ ìpàdé, ni kí Árónì ti tan iná náà níwájú Olúwa, láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀ lójojúmọ́. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀.

4. Àwọn Àtùpà tí wọ́n wà lórí ojúlówó ọ̀pá àtùpà tí a fi wúrà ṣe níwájú Olúwa ni kí ó máa jó lójojúmọ́.

5. “Mú ìyẹ̀fun dáradára, kí o sì ṣe ìṣù àkàrà méjìlá, kí o lo ìdáméjì nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n ẹfà (èyí jẹ́ lítà mẹ́rin ààbọ̀) fún ìṣù kọ̀ọ̀kan.

6. Tò wọ́n sí ọ̀nà ìlà méjì, mẹ́fàmẹ́fà ní ìlà kọ̀ọ̀kan lórí tábìlì tí a fi ojúlówó gòólù bọ̀. Èyí tí ó wà níwájú Olúwa.

7. Ẹ fi ojúlówó tùràrí sí ọnà kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ìpín ìrántí láti dípò àkàrà, àti láti jẹ ẹbọ ọrẹ iná sísun fún Olúwa.

8. Búrẹ́dì yìí ni kí ẹ gbé wá ṣíwájú Olúwa nígbàkugbà, lọ́sẹ̀ọ̀sẹ̀, nítorí tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú ayérayé.

9. Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ ló ni ín. Wọ́n gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ torí pé ó jẹ́ ipa tí ó mọ́ jùlọ ti ìpín wọn ojojúmọ́ nínú ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.”

Ìsọ̀rọ̀ Òdì Àti Ìjìyà Rẹ̀

10. Ọmọkùnrin kan wà tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọ Ísírẹ́lì baba rẹ̀ sì jẹ́ ará Éjíbítì. Ó jáde lọ láàrin àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ìjà sì ṣẹlẹ̀ nínú àgọ́ láàrin òun àti ọmọ Ísírẹ́lì kan.

11. Ọmọkùnrin arábìnrin Ísírẹ́lì náà sọ̀rọ̀ òdì sí orúkọ Olúwa pẹ̀lú èpè: Wọ́n sì mú-un tọ Mósè wá. (Orúkọ ìyá rẹ̀ ní Selomiti, ọmọbìnrin Débírì, ará Dánì).

12. Wọ́n fi í sínú àtìmọ́lé kí Olúwa to sọ ohun tí wọn yóò ṣe fún wọn.

13. Olúwa sì sọ fún Mósè pé:

14. “Mú asọ̀rọ̀òdì náà jáde wá sẹ́yìn àgọ́, kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ pé ó ṣépè gbé ọwọ́ wọn lórí ọkùnrin náà láti fi hàn pé ó jẹ̀bi. Lẹ́yìn náà ni kí gbogbo àpéjọpọ̀, sọ ọ́ ní òkúta pa.

15. Sọ fún àwọn ará Ísírẹ́lì pé: ‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣépè lé Ọlọ́run rẹ̀, yóò jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

16. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀òdì sí orúkọ Olúwa ni kí ẹ pa, kí gbogbo àpéjọpọ̀ sọ ọ́ ní òkúta pa, yálà àlejò ni tàbí ọmọbíbí Ísírẹ́lì, bí ó bá ti sọ̀rọ̀òdì sí orúkọ Olúwa, pípa ni kí ẹ pa á.

17. “ ‘Ẹni tí ó bá gba ẹmi ènìyàn pípa ni kí ẹ pa á.

18. Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn ẹlòmíràn, kí ó dá a padà—ẹ̀mí dípò ẹ̀mí.

19. Bí ẹnìkan bá pa ẹnìkejì rẹ̀ lára: ohunkóhun tí ó ṣe ni kí ẹ ṣe sí i.

20. Bí ó bá ṣẹ́ egungun ẹnìkan, egungun tirẹ̀ náà ni kí a ṣẹ́, bí ó bá fọ́ ojú ẹnìkan, ojú tirẹ̀ náà ni kí a fọ́, bí ó bá ká eyín ẹnìkan, eyín tirẹ̀ náà ni kí a ká. Bí ó ti pa ẹnìkejì lára náà ni kí ẹ pa òun náà lára.

21. Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹran ọ̀sìn gbọdọ̀ ṣe àtúnṣe ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn ni kí ẹ pa.

22. Òfin kan náà ló wà fún àlejò àti fún ọmọ Ísírẹ́lì. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’ ”

23. Nígbà náà ni Mósè sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, wọ́n sì mú asọ̀rọ̀òdì náà lọ sí ẹ̀yìn àgọ́: wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mósè.