orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹ́sítà 8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Àṣẹ Ọba Nítorí Awọn Júù

1. Ní ọjọ́ kan náà ni ọba Ṣérísésì fún Ésítà ayaba ní ilée Hámánì, ọ̀ta àwọn Júù. Módékáì sì wá síwájú ọba, nítorí Ẹ́sítà ti sọ bí ó ṣe jẹ́ sí ọba.

2. Ọba sì bọ́ òrùka dídán an rẹ̀, èyí tí ó ti gbà lọ́wọ́ọ Hámánì ó sì fi fún Módékáì, Ẹ́sítà sì yàn án gẹ́gẹ́ bí olóórí ilée Hámánì.

3. Ẹ́sítà sì tún bẹ ọba lórí ìkúnlẹ̀, pẹ̀lú omijé lójú. Ó bẹ̀ẹ́ kí ó fi òpin sí ètò búburú Hámánì ará Ágágì, èyí tí ó ti pète fún àwọn Júù.

4. Nígbà náà ni ọba na ọ̀pá aládé wúrà sí Ẹ́sítà ó sì dìde, ó dúró níwájúu rẹ̀.

5. Ó wí pé, “Bí ó bá wu ọba, tí ó bá sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ojú rere tí ó sì rò pé ohun tí ó dára ni láti ṣe, tí ó bá sì ní inú dídùn pẹ̀lúu mi, jẹ́ kí a kọ ìwé àṣẹ láti yí ète tí Hámánì ọmọ Hámédátà, ará Ágágì, tí ó kọ́ pàṣẹ pé kí a pa àwọn Júù tí wọ́n wà ní gbogbo àgbáyé ìjọba ọba run.

6. Nítorí báwo ni èmi yóò ṣe fara dàá tí èmi yóò sì rí kí ibi máa ṣubú lu àwọn ènìyàn mi? Báwo ni èmi yóò ṣe fara dàá, tí èmi yóò sì máa wo ìparun àwọn ìdíléè mi?”

7. Ọba Ṣéríṣésì dá Ẹ́sítà ayaba àti Módékáì aráa Júù náà lóhùn pé, “Nítorí Hámánì kọ lu àwọn aráa Júù, èmi ti fi ilée rẹ̀ fún Ẹ́sítà, wọ́n sì ti ṣo ó kọ́ sórí igi.

8. Nísinsin yìí, kọ ìwé àṣẹ mìíràn ní orúkọ ọba bí àwọn Júù ṣe jẹ́ pàtàkì sí ọ, kí o sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì dìí-nítorí kò sí àkọsílẹ̀ tí a bá ti kọ ní orúkọ ọba tí a sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì tí a lè yìí padà.”

9. Lẹ́ṣẹ̀ kan náà àwọn akọ̀wé ọba péjọ ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kẹta, oṣù sífánì. Wọ́n kọ gbogbo àṣẹ Módékáì sí àwọn Júù, àti sí àwọn alákòóṣo baálẹ̀ àti àwọn ọlọ́lá ìgbèríko mẹ́tadínláàdóje tí ó lọ láti Ińdíà títí ó fi dé kúsì. Kí a kọ àṣẹ náà ní ìlànà bí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọ̀wé àti bí èdè olúkúlùkù àti pẹ̀lú sí àwọn Júù ní ìlànà bí wọ́n ṣe ń kọ̀wé àti èdè e wọn.

10. Modékáì sì fi àṣẹ ọba Ṣéríṣésì kọ̀wé, ó sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì i rẹ̀, ó rán-an lọ ní kíákíá, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ ayaba, bí àṣà àwọn tí wọ́n ń gun ẹṣin tí ó yára, ní pàtàkì èyí tí a ń bọ́ fún ọba.

11. Àṣẹ ọba sì dé ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní gbogbo ìlú láti kó ara wọn jọ kí wọn sì dáàbò bo ara wọn; láti pa, láti run àti láti kọlu ogunkógun orílẹ̀ èdè kórílẹ̀ èdè kankan tàbí ìgbéríko tí ó bá fẹ́ kọ lù wọ́n, àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wọn; kí ẹ sì kó gbogbo ohun ìní àwọn ọ̀taa wọn.

12. Ọjọ́ tí a yàn fún àwọn Júù ní gbogbo agbégbé ọba Ṣéríṣésì láti ṣe nǹkan yìí ni ọjọ́ kẹtàlá èyí tí í ṣe oṣu kejìlá, oṣù Ádárì.

13. Ọkàn ìwé àṣẹ náà ni kí a gbé jáde gẹ́gẹ́ bí òfin ní gbogbo ìgbéríko kí ẹ sì jẹ́ kí ó di mímọ̀ fún gbogbo ènìyàn ìlú nítorí àwọn Júù yóò leè múra ní ọjọ́ náà láti gbẹ̀san fún ara wọn lára àwọn ọ̀taa wọn.

14. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ ayaba bí àṣà tí wọ́n ń gun ẹṣin ọba, sáré jáde, wọ́n sáré lọ nípa àṣẹ ọba. A sì tún gbé àṣẹ náà jáde ní ilé ìṣọ́ ti Ṣúṣà.

15. Módékáì sì kúrò níwájú ọba, ó wọ aṣọ aláró àti funfun, ó dé adé e wúrà ńlá pẹ̀lú ìgbànú eléṣèé àlùkò dáradára, ìlú Ṣúṣà sì ṣe àjọyọ̀ ńlá.

16. Àsìkò ìdùnú àti ayọ̀, inú dídùn àti ọlá ni ó jẹ́ fún àwọn Júù.

17. Ní gbogbo ìgbèríko àti ní gbogbo ìlú, ní gbogbo ibi tí àṣẹ ọba dé, ni ayọ̀ àti inú dídùn ti wà láàrin àwọn Júù, wọ́n sì ń ṣe àsè àti àjọyọ̀. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú tó kù sọ ara wọn di Júù nítorí ẹ̀rù àwọn Júù bà wọ́n.