orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹ́sítà 6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ọba Bu Ọlá Fún Módékáì

1. Ní òru ọjọ́ náà ọba kò le è ṣùn; nítorí náà, ó pàṣẹ kí wọn mú ìwé ìrántí wá, àkọsílẹ̀ ìjọba rẹ̀, wọ́n mú un wá wọ́n sì kàá síi létí.

2. Wọ́n rí àkọsílẹ̀ níbẹ̀ pé Módékáì tí sọ àṣírí Bígítanà àti Térésì, àwọn ìjòyè ọba méjì tí wọ́n ń ṣọ́ ẹnu ọ̀nà, tí wọ́n ń gbérò láti pa ọba Ṣérísésì.

3. Ọba béèrè pé, “Kí ni ọlá àti iyì tí Módékáì ti gbà fún èyí?”Àwọn ìránṣẹ́ẹ rẹ̀ sì dáhùn pé, “Kò tíì sí ohun tí a ṣe fún-un.”

4. Ọba wí pé, “Taa ni ó wà nínú àgbàlá?” Nísinsin yìí Hámánì ṣẹ̀ṣẹ̀ wọ àgbàlá ìta ààfin ni láti sọ fún ọba nípa ṣíṣo Módékáì lórí igi tí ó ti rì fún-un.

5. Àwọn ìránṣẹ́ẹ rẹ̀ sì dáhùn pé, “Hámánì ni ó wà níbẹ̀ ó dúró sí inú àgbàlá.”Ọba pàṣẹ pé, “Ẹ mú un wọlé wá.”

6. Nígbà tí Hámánì wọlé, ọba béèrè lọ́wọ́ọ rẹ̀ pé, “Kí ni kí a ṣe fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti bu ọlá fún?”Nísinsìnyìí Hámánì sì ro èyí fúnra rẹ̀ pé, “Taa ni ó wà níbẹ̀ tí ọba fẹ́ dá lọ́lá ju èmi lọ?”

7. Nítorí náà ó dá ọba lóhùn pé, “Fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá,

8. jẹ́ kí wọn kí ó mú aṣọ ọba èyí tí ọba ń wọ̀ àti ẹṣin tí ọba má a ń gùn, pẹ̀lú ọ̀kan lára adé ọba kí a fi dé e ní orí.

9. Jẹ́ kí a fí aṣọ àti ẹṣin lé ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ọba tí ó ga jùlọ lọ́wọ́, kí wọn wọ aṣọ náà fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá, kí wọn sì sìn-ín gun ẹṣin jákèjádò gbogbo ìgboro ìlú, kí wọn má a kéde níwájúu rẹ̀ pé, ‘Èyí ni a ṣe fún ọkùnrin náà ẹni tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá!’ ”

10. Ọba pàṣẹ fún Hámánì pé, “Lọ lẹ́ṣẹ̀ kan náà. Mú aṣọ náà àti ẹṣin kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ṣe sọ fún Módékáì araa Júù, ẹni tí ó jókòó sí ẹnu ọ̀nà ọba. Má ṣe fi ohunkóhun sílẹ̀ nínú ohun tí o ti yàn.”

11. Bẹ́ẹ̀ ni Hámánì ṣe mú aṣọ àti ẹṣin náà. Ó fi wọ Módékáì, Módékáì sì wà lórí ẹṣin jákèjádò gbogbo ìgboro ìlú, ó sì ń kéde níwájúu rẹ̀ pé, “Èyí ni a ó ṣe fún ọkùnrin náà ẹni tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá!”

12. Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Módékáì padà sí ẹnu ọ̀nà ọba. Ṣùgbọ́n Hámánì ṣáré lọ ilé, ó sì bo oríi rẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́,

13. Ó sì sọ ohun gbogbo tí ó ṣẹlẹ̀ síi fún Ṣérésì ìyàwóo rẹ̀ àti àwọn ọ̀rẹ́ẹ rẹ̀.Àwọn olùbádámọ̀ràn an rẹ̀ àti ìyàwó o rẹ̀ sọ fún-un pé, “Níwọ̀n ìgbà tí Módékáì ti jẹ́ ẹ̀yà Júù, níwájú ẹni tí ìṣubúu rẹ̀ ti bẹ̀rẹ̀, ìwọ kò lè rí ẹ̀yìn in rẹ̀—dájúdájú ìwọ yóò parun!”

14. Bí wọ́n ṣe ń báa sọ̀rọ̀, àwọn ìwẹ̀fà ọba wọlé, wọ́n sì kán Hámánì lójú láti lọ sí ibi àṣè tí Ẹ́sítà ti pèsè.