Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 23:15-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Àní pẹpẹ tí ó wà ní Bétélì ibi gíga tí Jéróbóámù ọmọ Nébátí dá. Tí ó ti fa Ísírẹ́lì láti ṣẹ̀—Àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì ṣun òpó Áṣérà pẹ̀lú.

16. Nígbà náà, Jòṣíà wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn iṣà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.

17. Ọba sì béèrè, pé “Kí ni ọwọ́n iṣà òkú yẹn tí mo rí?”Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí iṣà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Júdà, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Bétélì, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”

18. “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Ṣamáríà.

19. Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Bétélì, Jòṣíàh sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Ísírẹ́lì ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Ṣamáríà, tí ó ti mú Olúwa bínú.

20. Jòṣíáyà dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì ṣun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jérúsálẹ́mù.

21. Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé: “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”

22. Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Júdà tí ó tọ́ Ísírẹ́lì, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì àti àwọn ọba Júdà. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.

23. Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Jòṣíà, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jérúsálẹ́mù.

24. Síwájú sí, Jòsíáyà sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Júdà àti ní Jérúsálẹ́mù. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hílíkíyà àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.

25. Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Jóṣíáyà tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Móṣè.

26. Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Júdà, nítorí gbogbo èyí tí Mánásè ti ṣe láti mú un bínú.

27. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Júdà kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Ísírẹ́lì, èmi yóò sì kó Jérúsálẹ́mù, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’ ”

28. Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jòṣíà, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Júdà?

29. Nígbà tí Jòṣíà jẹ́ ọba, Fáráò Nékò ọba Éjíbítì gòkè lọ sí odò Yúfúrátè láti lọ ran ọba Ásíríà lọ́wọ́. Ọba Jòṣíáyà jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Nékò dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Mégídò.

Ka pipe ipin 2 Ọba 23