orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 14 BIBELI MIMỌ (BM)

1. “Ẹnikẹ́ni tí obinrin bá bí, ọlọ́jọ́ kúkúrú ni,ó sì kún fún ìpọ́njú.

2. Yóo kọ́ yọ bí òdòdó, lẹ́yìn náà yóo sì rẹ̀ dànù.Yóo kọjá lọ bí òjìji, kò sì ní sí mọ́.

3. Ṣé irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni o dojú kọ,tí ò ń bá ṣe ẹjọ́?

4. Ta ló lè mú ohun mímọ́ jádeláti inú ohun tí kò mọ́?Kò sí ẹni náà.

5. Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá ọjọ́ fún un,tí o mọ iye oṣù rẹ̀,tí o sì ti pa ààlà tí kò lè rékọjá.

6. Mú ojú rẹ kúrò lára rẹ̀, kí ó lè sinmi,kí ó sì lè gbádùn ọjọ́ ayé rẹ̀ bí alágbàṣe.

7. “Nítorí pé ìrètí ń bẹ fún igi tí wọn gé,yóo tún pada rúwé,ẹ̀ka rẹ̀ kò sì ní ṣe aláìsọ.

8. Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ògbólógbòó ninu ilẹ̀,tí kùkùté rẹ̀ sì kú,

9. bí ó bá ti gbóòórùn omi, yóo sọ,yóo sì yọ ẹ̀ka bí ọ̀dọ́ irúgbìn.

10. Ṣugbọn bí eniyan bá kú, a óo tẹ́ ẹ sinu ibojì,bí ó bá ti gbẹ́mìí mì, ó di aláìsí.

11. Bí adágún omi tíí gbẹ,ati bí odò tíí ṣàn lọ, tí sìí gbẹ,

12. bẹ́ẹ̀ ni eniyan ṣe é sùn,tí kì í sìí jí mọ́,títí tí ọ̀run yóo fi kọjá lọ, kò ní jí,tabi kí ó tilẹ̀ rúnra láti ojú oorun.

13. Ìbá sàn kí o fi mí pamọ́ sinu ibojì,kí o pa mí mọ́ títí inú rẹ yóo fi rọ̀,ò bá dá àkókò fún mi, kí o sì ranti mi.

14. Bí eniyan bá kú, ǹjẹ́ yóo tún jí mọ́?N óo dúró ní gbogbo ọjọ́ làálàá mi,n óo máa retí, títí ọjọ́ ìdáǹdè mi yóo fi dé.

15. O óo pè mí, n ó sì dá ọ lóhùn,o óo máa ṣe àfẹ́rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

16. Nígbà náà, o óo máa tọ́ ìṣísẹ̀ mi,o kò sì ní ṣọ́ àwọn àṣìṣe mi.

17. O óo di àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mi sinu àpò,o óo sì bo àwọn àìdára mi mọ́lẹ̀.

18. “Ṣugbọn òkè ńlá ṣubú, ó sì rún wómúwómú,a sì ṣí àpáta nídìí kúrò ní ipò rẹ̀.

19. Bí omi ṣe é yìnrìn òkúta,tí àgbàrá sì í wọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀ lọ,bẹ́ẹ̀ ni o óo ṣe sọ ìrètí eniyan di òfo.

20. O ṣẹgun rẹ̀ títí lae, ó sì kọjá lọ,o yí àwọ̀ rẹ̀ pada, o sì mú kí ó lọ.

21. Wọ́n dá àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́lá, ṣugbọn kò mọ̀,a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, sibẹ kò rí i.

22. Ìrora ara rẹ̀ nìkan ló mọ̀,ọ̀fọ̀ ara rẹ̀ nìkan ni ó ń ṣe.”