orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 26 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Jobu bá dáhùn pé,

2. “Ìrànlọ́wọ́ wo ni ẹ ti ṣe fún àwọn tí wọn kò lágbára?Aláìlera wo ni ẹ ti gbàlà?

3. Ìmọ̀ràn wo ni ẹ ti fún àwọn aláìgbọ́n?Irú òye wo ni ẹ fihàn wọ́n?

4. Ta ló ń kọ yín ni ohun tí ẹ̀ ń sọ wọnyi?Irú ẹ̀mí wo sì ní ń gba ẹnu yín sọ̀rọ̀?

5. “Àwọn òkú wárìrì nísàlẹ̀.Omi ati àwọn olùgbé inú rẹ̀ pẹlu ń gbọ̀n rìrì.

6. Kedere ni isà òkú rí níwájú Ọlọrun,bẹ́ẹ̀ ni ìparun kò farasin.

7. Ó na ìhà àríwá sórí òfuurufú,ó sì so ayé rọ̀ sí òfuurufú.

8. Ó di omi papọ̀ ninu ìkùukùu rẹ̀ tí ó nípọn,sibẹ ìkùukùu kò fà ya.

9. Ó dí ojú òṣùpá,ó sì fi ìkùukùu bò ó.

10. Ó ṣe òbìrìkítí kan sórí omi,ó fi ṣe ààlà láàrin òkùnkùn ati ìmọ́lẹ̀.

11. Àwọn òpó ọ̀run mì tìtì,wọ́n sì wárìrì nítorí ìbáwí rẹ̀.

12. Nípa agbára rẹ̀, ó mú kí òkun parọ́rọ́,nípa ìmọ̀ rẹ̀, ó pa Rahabu.

13. Ó fi afẹ́fẹ́ ṣe ojú ọ̀run lọ́ṣọ̀ọ́;ọwọ́ ló fi pa ejò tí ń fò.

14. Ṣugbọn kékeré nìyí ninu agbára rẹ̀,díẹ̀ ni a tíì gbọ́ nípa iṣẹ́ rẹ̀!Nítorí náà ta ló lè mọ títóbi agbára rẹ̀?”