orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 9 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Jobu dáhùn pé:

2. “Lóòótọ́, mo mọ̀ pé bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ rí,ṣugbọn báwo ni ẹlẹ́ran ara ṣe lè jẹ́ olódodo níwájú Ọlọrun?

3. Bí eniyan tilẹ̀ fẹ́ bá a jiyàn,olúwarẹ̀ kò ní lè dáhùn ẹyọ kan ninu ẹgbẹrun ìbéèrè tí yóo bèèrè.

4. Ọgbọ́n rẹ̀ jinlẹ̀,agbára rẹ̀ sì pọ̀.Ta ló tó ṣe oríkunkun sí i kí ó mú un jẹ?

5. Ẹni tí ó ṣí àwọn òkè nídìí, ninu ibinu rẹ̀;tí wọn kò sì mọ ẹni tí ó bì wọ́n ṣubú.

6. Ó ti ayé kúrò ní ipò rẹ̀,àwọn òpó rẹ̀ sì wárìrì.

7. Ó pàṣẹ fún oòrùn,oòrùn kò sì yọ;ó sé àwọn ìràwọ̀ mọ́lé;

8. òun nìkan ṣoṣo ni ó dá ojú ọ̀run tẹ́ bí aṣọ,tí ó sì tẹ ìgbì omi òkun mọ́lẹ̀.

9. Ó dá àwọn ìràwọ̀ sójú ọ̀run:Beari, Orioni, ati Pileiadesiati àwọn ìràwọ̀ ìhà gúsù.

10. Ó ṣe àwọn ohun ńlá tí ó kọjá òye ẹ̀dá,ati àwọn iṣẹ́ ìyanu tí kò ní òǹkà.

11. Ó gba ẹ̀gbẹ́ mi kọjá, n kò rí i,ó ń kọjá lọ, n kò sì mọ̀.

12. Wò ó! Ó já àwọn ohun tí ó wù ú gbà,ta ló lè dá a dúró?Ta ló tó bi í pé, ‘Kí ni ò ń ṣe?’

13. “Ọlọrun kò ní dáwọ́ ibinu rẹ̀ dúró,yóo fi ẹsẹ̀ tẹ àwọn olùrànlọ́wọ́ Rahabu mọ́lẹ̀.

14. Báwo ni mo ṣe lè bá a rojọ́?Kí ni kí n sọ?

15. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́bi,sibẹsibẹ n kò lè dá a lóhùn.Ẹ̀bẹ̀ nìkan ni mo lè bẹ̀ fún àánú,lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ẹ̀sùn kàn mí.

16. Bí mo bá pè é pé kó wá gbọ́,tí ó sì dá mi lóhùn,sibẹ n kò lè gbàgbọ́ pé yóo dẹtí sílẹ̀ gbọ́rọ̀ mi.

17. Nítorí pé ó ti fi ìjì tẹ̀ mí mọ́lẹ̀,ó sì sọ egbò mi di pupọ láìnídìí;

18. kò ní jẹ́ kí n mí,ìbànújẹ́ ni ó fi kún ọkàn mi.

19. Bí ó bá ṣe ti pé kí á dán agbára wò ni,agbára rẹ̀ pọ̀ tayọ!Bí ó bá sì jẹ́ pé ti ọ̀rọ̀ ẹ̀tọ́,ta ló lè pè é lẹ́jọ́?

20. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́bi,sibẹsibẹ ọ̀rọ̀ ẹnu mi yóo di ẹ̀bi rù mí;bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́ṣẹ̀,sibẹsibẹ yóo fihàn pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni mí.

21. N kò lẹ́bi,sibẹ n kò ka ara mi kún,ayé sú mi.

22. Kò sí ìyàtọ̀ lójú rẹ̀,nítorí náà ni mo fi wí pé,ati ẹlẹ́bi ati aláìlẹ́bi ni ó ti parun.

23. Nígbà tí nǹkan burúkú bá ṣẹlẹ̀,tí ó já sí ikú òjijì,a máa fi aláìṣẹ̀ ṣe ẹlẹ́yà ninu ìdààmú wọn.

24. A ti fi ayé lé àwọn ẹni ibi lọ́wọ́,ó ti di àwọn adájọ́ rẹ̀ lójú.Bí kì í bá ṣe òun Ọlọrun,ta ló tún tó bẹ́ẹ̀?

25. “Ọjọ́ ayé mi ń sáré lọ tete,kò sí ẹyọ ọjọ́ kan tí ó dára ninu wọn.

26. Wọ́n sáré kọjá lọ bíi koríko ojú omi,bí ẹyẹ idì tí ń fò fẹ̀ẹ̀ lọ bá ohun tí ó fẹ́ pa.

27. Bí mo bá sọ pé kí n gbàgbé ìráhùn mi,kí n sì tújúká;kí n má ronú mọ́;

28. ẹ̀rù ìrora mi á bẹ̀rẹ̀ sí bà mí,nítorí mo mọ̀ pé o kò ní gbà pé n kò dẹ́ṣẹ̀.

29. Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá mi lẹ́bi,kí ni mo tún ń ṣe wahala lásán fún?

30. Ọṣẹ yòówù tí mo lè fi wẹ̀,kódà kí n fi omi yìnyín fọ ọwọ́,

31. sibẹ o óo tì mí sinu kòtò ìdọ̀tí.Kódà n óo di ohun ìríra sí aṣọ ara mi.

32. Ọlọrun kì í ṣe eniyan bíì mi,tí mo fi lè fún un lésì,tí a fi lè jọ rojọ́ ní ilé ẹjọ́.

33. Kò sí ẹnìkẹta láàrin àwa mejeeji,tí ó lè dá wa lẹ́kun.

34. Kí ó sọ pàṣán rẹ̀ sílẹ̀,kí ó má nà mí mọ́!Kí ìbẹ̀rù rẹ̀ má sì pá mi láyà mọ́!

35. Kí n baà le sọ̀rọ̀ láìbẹ̀rù,nítorí mo mọ inú ara mi.