orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 4 BIBELI MIMỌ (BM)

Ìfọ̀rọ̀wérọ̀ Kinni

1. Nígbà náà ni Elifasi, ará Temani, dá Jobu lóhùn, ó ní:

2. “Bí eniyan bá bá ọ sọ̀rọ̀,ṣé kò ní bí ọ ninu?Àbí eniyan ha lè dákẹ́ bí?

3. O ti kọ́ ọpọlọpọ eniyan,o ti fún aláìlera lókun.

4. O ti fi ọ̀rọ̀ gbé àwọn tí wọn ń ṣubú ró,ọ̀rọ̀ rẹ ti fún orúnkún tí ń yẹ̀ lọ lágbára.

5. Ṣugbọn nisinsinyii tí ọ̀rọ̀ kàn ọ́,o kò ní sùúrù;Ó dé bá ọ, ìdààmú bá ọ.

6. Ṣé ìbẹ̀rù Ọlọrun kò tó ìgboyà fún ọ?Àbí ìwà òdodo rẹ kò fún ọ ní ìrètí?

7. “Ìwọ náà ronú wò,ṣé aláìṣẹ̀ kan ṣègbé rí?Tabi olódodo kan parun rí?

8. Bí èmi ti rí i sí ni pé,ẹni tí ó kọ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́ ebè,tí ó sì gbin wahala,yóo kórè ìyọnu.

9. Èémí Ọlọrun níí pa wọ́n run,ninu ibinu rẹ̀, wọ́n a sì ṣègbé.

10. Ọlọrun fi òpin sí igbe kinniun,ati bíbú tí kinniun ń bú ramúramù,ó sì wọ́ àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun léyín.

11. Kinniun alágbára a máa kú,nítorí àìrí ẹran pa jẹ,àwọn ọmọ abo kinniun a sì fọ́nká.

12. “Nisinsinyii wọ́n fọ̀rọ̀ kan tó mi létímo gbọ́ wúyẹ́-wúyẹ́ rẹ̀.

13. Ninu ìran lóru,nígbà tí àwọn eniyan sùn fọnfọn,

14. ìbẹ̀rùbojo mú mi,gbogbo ara mi sì ń gbọ̀n rìrì.

15. Ẹ̀mí kan kọjá fìrí níwájú mi,gbogbo irun ara mi sì dìde.

16. Ó dúró jẹ́ẹ́,ṣugbọn n kò mọ̀ bí ó ti rí.Mo ṣá rí kinní kan tí ó dúró;gbogbo nǹkan parọ́rọ́,nígbà náà ni mo gbọ́ ohùn kan tí ó wí pé,

17. ‘Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè jẹ́ olódodo níwájú Ọlọrun?Tabi kí eniyan jẹ́ mímọ́ níwájú Ẹlẹ́dàá rẹ̀?

18. Nígbà tí ó jẹ́ pé,Ọlọrun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn iranṣẹ rẹ̀,a sì máa bá àṣìṣe lọ́wọ́ àwọn angẹli rẹ̀;

19. mélòó mélòó wá ni eniyan tí a fi amọ̀ mọ,tí ìpìlẹ̀ wọn jẹ́ erùpẹ̀,tí a lè pa bíi kòkòrò lásánlàsàn.

20. Eniyan lè wà láàyè ní òwúrọ̀kí ó kú kí ó tó di ọjọ́ alẹ́,wọn a parun títí laeláìsí ẹni tí yóo bìkítà.

21. Bí a bá gba gbogbo ohun tí wọ́n fẹ̀mí tẹ̀,ṣé wọn kò ní kú bí aláìgbọ́n?’