orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 28 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Àwọn eniyan burúkú a máa sá,nígbà tí ẹnikẹ́ni kò lé wọn,ṣugbọn olódodo a máa láyà bíi kinniun.

2. Bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀,léraléra ni wọ́n ó máa jọba,ṣugbọn bí orílẹ̀-èdè kan bá ní àwọn eniyan tí wọn ní òye ati ìmọ̀,yóo wà fún ìgbà pípẹ́.

3. Talaka tí ń ni aláìní láradàbí òjò líle tí ó ba nǹkan ọ̀gbìn jẹ́.

4. Àwọn tí wọ́n kọ òfin sílẹ̀ni wọ́n máa ń yin àwọn eniyan burúkú,ṣugbọn àwọn tí wọn ń pa òfin mọ́ máa ń dojú ìjà kọ wọ́n.

5. Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn eniyan burúkú,ṣugbọn ó yé àwọn tí ń wá OLUWA yékéyéké.

6. Talaka tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inúsàn ju ọlọ́rọ̀ tí ń hùwà àgàbàgebè lọ.

7. Ọlọ́gbọ́n ọmọ ni ọmọ tí ó pa òfin mọ́,ṣugbọn ẹni tí ń bá àwọn wọ̀bìà rìn, ń dójúti baba rẹ̀.

8. Ẹni tí ó ń fi kún ọrọ̀ rẹ̀ nípa gbígba èléati èrè jíjẹ ní ọ̀nà èrú,ń kó ọrọ̀ náà jọ fún ẹni tí yóo ṣàánú àwọn talaka.

9. Ẹni tí ó kọ etí dídi sí òfin Ọlọrun,adura rẹ̀ pàápàá yóo di ìríra sí Ọlọ́run.

10. Ẹni tí ó ṣi olódodo lọ́nà lọ sinu ibi,yóo já sinu kòtò tí òun fúnrarẹ̀ gbẹ́ sílẹ̀,ṣugbọn aláìlẹ́bi eniyan yóo jogún ire.

11. Ọlọ́rọ̀ gbọ́n lójú ara rẹ̀,ṣugbọn talaka tí ó gbọ́n yóo rídìí rẹ̀.

12. Nígbà tí olódodo bá borí, àwọn eniyan á yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀,ṣugbọn nígbà tí ìkà bá dìde, àwọn eniyan á sá pamọ́.

13. Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣe rere,ṣugbọn ẹni tí ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,tí ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, yóo rí àánú gbà.

14. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó ń bẹ̀rù OLUWA nígbà gbogbo,ṣugbọn ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le yóo bọ́ sinu ìyọnu.

15. Ọba burúkú tí ó jọba lórí àwọn talaka,dàbí kinniun tí ń bú ramúramù,tabi ẹranko beari tí inú ń bí.

16. Ìkà, aninilára ni olórí tí kò ní òye,ṣugbọn ẹ̀mí ẹni tí ó bá kórìíra à ń jèrè lọ́nà èrú yóo gùn.

17. Bí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan bá ń da eniyan láàmú,yóo di ìsáǹsá ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀,kí ẹnikẹ́ni má ṣe ràn án lọ́wọ́.

18. Ẹni tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inú yóo rí ìgbàlà,ṣugbọn ẹni tí ń rìn ségesège yóo ṣubú sinu kòtò.

19. Ẹni tí ń ṣiṣẹ́ oko dáradára, yóo ní oúnjẹ pupọ,ṣugbọn ẹni tí ń fi àkókò rẹ̀ ṣòfò yóo di talaka.

20. Olóòótọ́ yóo ní ibukun lọpọlọpọ,ṣugbọn ẹni tí ń kánjú àtilówó, kò ní lọ láìjìyà.

21. Ojuṣaaju kò dára,sibẹ oúnjẹ lè mú kí eniyan ṣe ohun tí kò tọ́.

22. Ahun a máa sáré ati ní ọrọ̀,láìmọ̀ pé òṣì ń bọ̀ wá ta òun.

23. Ẹni tí ó bá eniyan wí,yóo rí ojurere níkẹyìn,ju ẹni tí ń pọ́n eniyan lọ.

24. Ẹni tí ó ja ìyá tabi baba rẹ̀ lólè,tí ó ní, “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀”,ẹlẹgbẹ́ apanirun ni.

25. Olójúkòkòrò eniyan a máa dá ìjà sílẹ̀,ṣugbọn ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo ṣe rere.

26. Òmùgọ̀ ni ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀,ẹni tí ń fi ọgbọ́n rìn yóo là.

27. Ẹni tí ó ta talaka lọ́rẹ kò ní ṣe aláìní,ṣugbọn ẹni tí ó fojú pamọ́ fún wọn, yóo gba ègún.

28. Nígbà tí àwọn eniyan burúkú bá dìde,àwọn eniyan á sá pamọ́,ṣugbọn nígbà tí wọ́n bá parun, olódodo á pọ̀ sí i.