orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 15 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ a máa mú kí ibinu rọlẹ̀,ṣugbọn ọ̀rọ̀ líle níí ru ibinu sókè.

2. Lẹ́nu ọlọ́gbọ́n ni ọ̀rọ̀ ìmọ̀ ti ń jáde,ṣugbọn òmùgọ̀ a máa sọ̀rọ̀ agọ̀.

3. Ojú OLUWA wà níbi gbogbo,ó ń ṣọ́ àwọn eniyan burúkú ati àwọn eniyan rere.

4. Ọ̀rọ̀ tí a fi pẹ̀lẹ́ sọ dàbí igi ìyè,ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn a máa bani lọ́kàn jẹ́.

5. Òmùgọ̀ ọmọ á kẹ́gàn ìtọ́sọ́nà baba rẹ̀,ṣugbọn ọmọ tí ó gbọ́ ìkìlọ̀, ọlọ́gbọ́n ni.

6. Ilé olódodo kún fún ọpọlọpọ ìṣúra,ṣugbọn kìkì ìdààmú ni àkójọ èrè eniyan burúkú.

7. Ẹnu ọlọ́gbọ́n a máa tan ìmọ̀ kálẹ̀,ṣugbọn ti òmùgọ̀ kò rí bẹ́ẹ̀.

8. Ohun ìríra ni ẹbọ eniyan burúkú lójú OLUWA,ṣugbọn adura olódodo jẹ́ ìdùnnú rẹ̀.

9. OLUWA kórìíra ìwà àwọn eniyan burúkú,ṣugbọn ó fẹ́ràn àwọn tí ń hùwà òdodo.

10. Ìbáwí pupọ ń bẹ fún ẹni tí ó yapa kúrò ní ọ̀nà rere,ẹni tí ó bá kórìíra ìbáwí yóo kú.

11. Isà òkú ati ìparun kò pamọ́ lójú OLUWA,mélòó-mélòó ni ọkàn eniyan.

12. Inú pẹ̀gànpẹ̀gàn kì í dùn sí ìbáwí,kì í bèèrè ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ọlọ́gbọ́n.

13. Inú dídùn a máa múni dárayá,ṣugbọn ìbànújẹ́ a máa mú kí ojú eniyan rẹ̀wẹ̀sì.

14. Ẹni tí ó ní òye a máa wá ìmọ̀,ṣugbọn agọ̀ ni oúnjẹ òmùgọ̀.

15. Gbogbo ọjọ́ ayé ẹni tí a ni lára kún fún ìpọ́njú,ṣugbọn ojoojumọ ni ọdún fún ẹni tí inú rẹ̀ dùn.

16. Ó sàn kí á jẹ́ talaka, kí á sì ní ìbẹ̀rù OLUWA,ju kí á jẹ́ ọlọ́rọ̀, kí á sì kún fún ìyọnu lọ.

17. Ọbẹ̀ ẹ̀fọ́ pẹlu ìfẹ́,sàn ju ẹran mààlúù tòun ti ìkórìíra lọ.

18. Onínúfùfù a máa rú ìjà sókè,ṣugbọn onínútútù a máa pẹ̀tù sí ibinu.

19. Ẹ̀gún kún bo ọ̀nà ọ̀lẹ,ṣugbọn ọ̀nà olódodo dàbí òpópó tí ń dán.

20. Ọlọ́gbọ́n ọmọ a máa mú inú baba rẹ̀ dùn,ṣugbọn òmùgọ̀ ọmọ níí kẹ́gàn ìyá rẹ̀.

21. Ayọ̀ ni ìwà òmùgọ̀ jẹ́ fún aláìgbọ́n,ṣugbọn ẹni tí ó ní òye a máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́.

22. Àìsí ìmọ̀ràn a máa mú kí ètò dàrú,ṣugbọn ọpọlọpọ ìmọ̀ràn a máa mú kí ó yọrí sí rere.

23. Ìdáhùn kíkún a máa fúnni láyọ̀,kí ọ̀rọ̀ bọ́ sí àsìkò dára lọpọlọpọ!

24. Ọ̀nà ọlọ́gbọ́n lọ tààrà sinu ìyè,kí ó má baà bọ́ sinu isà òkú.

25. OLUWA a máa wó ilé agbéraga,ṣugbọn ó ṣe àmójútó ààlà opó.

26. Ohun ìríra ni èrò ọkàn ẹni ibi lójú OLUWA,ṣugbọn ọrọ̀ àwọn ẹni mímọ́ jẹ́ dídùn inú rẹ̀.

27. Àwọn tí ń ṣojúkòkòrò èrè àìtọ́ ń kó ìyọnu bá ilé wọn,ṣugbọn àwọn tí wọn kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóo yè.

28. Olódodo a máa ronú kí ó tó fèsì ọ̀rọ̀,ṣugbọn ọ̀rọ̀ burúkú níí máa jáde lẹ́nu àwọn eniyan burúkú.

29. OLUWA jìnnà sí eniyan burúkú,ṣugbọn a máa gbọ́ adura olódodo.

30. Ọ̀yàyà a máa mú inú dùn,ìròyìn ayọ̀ a sì máa mú ara yá.

31. Ẹni tó gbọ́ ìbáwí rereyóo wà láàrin àwọn ọlọ́gbọ́n.

32. Ẹni tí kò náání ìbáwí tàbùkù ara rẹ̀,ṣugbọn ẹni tí ó bá gba ìmọ̀ràn yóo ní òye.

33. Ìbẹ̀rù OLUWA níí kọ́ni lọ́gbọ́n,ìwà ìrẹ̀lẹ̀ níí ṣáájú iyì.