orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 22 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Orúkọ rere dára láti yàn ju ọrọ̀ pupọ lọ,kí á rí ojurere sì dára ju kí á ní fadaka ati wúrà lọ.

2. Ọlọ́rọ̀ ati talaka pàdé,OLUWA ló dá ekinni-keji wọn.

3. Ọlọ́gbọ́n rí ibi, ó farapamọ́,ṣugbọn òpè ń bá tirẹ̀ lọ láìbìkítà,ó sì kó sinu ìyọnu.

4. Èrè ìrẹ̀lẹ̀ ati ìbẹ̀rù OLUWA ni ọrọ̀, ọlá, ati ìyè.

5. Ẹ̀gún ati tàkúté ń bẹ lọ́nà àwọn ẹlẹ́tàn,ẹni tí ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóo jìnnà sí wọn.

6. Tọ́ ọmọ rẹ sí ọ̀nà tí ó yẹ kí ó máa rìn,bí ó bá dàgbà tán, kò ní kúrò ninu rẹ̀.

7. Ọlọ́rọ̀ máa ń jọba lé talaka lórí,ẹni tí ó lọ yá owó sì ni ẹrú ẹni tí ó yá a lówó.

8. Ẹni tí ó bá gbin aiṣododo yóo kórè ìdààmú,pàṣán ibinu rẹ̀ yóo sì parun.

9. Olójú àánú yóo rí ibukun gbà,nítorí pé ó ń fún talaka ninu oúnjẹ rẹ̀.

10. Lé pẹ̀gànpẹ̀gàn síta, ìjà yóo rọlẹ̀,asọ̀ ati èébú yóo sì dópin.

11. Ẹni tí ó fẹ́ ọkàn mímọ́,tí ó sì ní ọ̀rọ̀ rere lẹ́nu yóo bá ọba ṣọ̀rẹ́.

12. Ojú OLUWA ń ṣọ́ ìmọ̀ tòótọ́,ṣugbọn a máa yí ọ̀rọ̀ àwọn alaigbagbọ po.

13. Ọ̀lẹ a máa sọ pé, “Kinniun wà níta!Yóo pa mí jẹ lójú pópó!”

14. Ẹnu alágbèrè obinrin dàbí kòtò ńlá,ẹni tí OLUWA bá ń bínú sí níí já sinu rẹ̀.

15. Ìwà agídí dì sí ọkàn ọmọde,ṣugbọn pàṣán ìbáwí níí lé e jáde.

16. Ẹni tí ó ni talaka lára kí ó lè ní ohun ìní pupọ,tabi tí ó ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ yóo pada di talaka.

Ọgbọ̀n Gbolohun tí Ọlọ́gbọ́n Sọ

17. Tẹ́tí rẹ sílẹ̀ kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n,kí o sì fi ọkàn sí ẹ̀kọ́ mi,

18. nítorí yóo dára tí o bá pa wọ́n mọ́ lọ́kàn rẹ,tí o sì ń fi wọ́n ṣe ọ̀rọ̀ sọ jáde.

19. Ìwọ ni mo sọ wọ́n di mímọ̀ fún lónìí, àní ìwọ,kí ó le jẹ́ pé OLUWA ni o gbẹ́kẹ̀lé.

20. Ṣebí mo ti kọ ọgbọ̀n àkọsílẹ̀ fún ọ lórí ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n,

21. láti fi ohun tí ó tọ̀nà tí ó sì jẹ́ òtítọ́ hàn ọ́,kí o lè fi ìdáhùn pípé fún ẹni tí ó rán ọ.

-1-

22. Má ja talaka lólè, nítorí pé ó jẹ́ talaka,má sì dájọ́ èké fún ẹni tí ara ń ni.

23. Nítorí OLUWA yóo gbèjà wọn,yóo fìyà jẹ àwọn tí wọn ń jẹ wọ́n níyà.

-2-

24. Má bá oníbìínú eniyan kẹ́gbẹ́,má sì bá onínúfùfù da nǹkan pọ̀.

25. Kí o má baà kọ́ ìwà rẹ̀,kí o sì fi tàkúté mú ara rẹ.

-3-

26. Má bá wọn ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tó fẹ́ yá owó,má bá wọn ṣe onídùúró fún onígbèsè.

27. Tí o kò bá rí owó san fún olówó,olówó lè pé kí wọn gba ibùsùn rẹ.

-4-

28. Má hú ohun tí àwọn baba ńlá rẹ rì mọ́lẹ̀,tí wọ́n fi pa ààlà kúrò.