orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 21 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Orísun omi ni ọkàn ọba lọ́wọ́ OLUWA,ibi tí ó bá wu Oluwa ni ó ń darí rẹ̀ sí.

2. Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó dára lójú ara rẹ̀,ṣugbọn ọkàn ni OLUWA ń wò.

3. Kí eniyan ṣe òdodo ati ẹ̀tọ́,sàn ju ẹbọ lọ lójú OLUWA.

4. Bíi fìtílà ẹni ibi ni gbígbé ojú gangan ati ìgbéraga,ẹ̀ṣẹ̀ sì ni wọ́n.

5. Dájúdájú èrò ẹni tí ó ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn yóo yọrí sí ọ̀pọ̀,ṣugbọn ẹni tí ó bá ń kánjú jù kò ní ní ànító.

6. Fífi èké kó ìṣúra jọdàbí lílé ìkùukùu, ó sì jẹ́ tàkúté ikú.

7. Ìwà ipá àwọn ẹni ibi ni yóo gbá wọn dànù,nítorí pé wọ́n kọ̀ láti ṣe òtítọ́.

8. Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún,ṣugbọn ìrìn aláìlẹ́bi a máa tọ́.

9. Ó sàn láti máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà,ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

10. Ibi ni ọkàn eniyan burúkú máa ń fẹ́,àwọn aládùúgbò rẹ̀ kì í sìí rí ojurere rẹ̀.

11. Ìjìyà ẹlẹ́yà a máa mú kí òpè gbọ́n,tí a bá ń kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo ní ìmọ̀ sí i.

12. Olódodo ṣàkíyèsí ilé eniyan burúkú,eniyan burúkú sì bọ́ sinu ìparun.

13. Ẹni tí ó kọ etí dídi sí igbe talaka,òun náà yóo kígbe, ṣugbọn kò ní rí ẹni dá a lóhùn.

14. Ẹ̀bùn tí a fúnni ní kọ̀rọ̀ a máa paná ibinu,àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a tì bọ abẹ́ aṣọ a máa paná ìjà.

15. Tí a bá ṣe ìdájọ́ òtítọ́, inú olódodo a dùn,ṣugbọn ìfòyà ni fún àwọn aṣebi.

16. Ẹni tí ó sá kúrò lọ́nà òyeyóo sinmi láàrin àwọn òkú.

17. Ẹni tí ó fẹ́ràn fàájì yóo di talaka,ẹni tí ó fẹ́ràn ọtí waini ati òróró kò ní lówó lọ́wọ́.

18. Eniyan burúkú ni yóo forí gba ibitíì bá dé bá olódodo.Alaiṣootọ ni yóo fara gba ìyà tí ó tọ́ sí olóòótọ́ inú.

19. Ó sàn láti máa gbé ààrin aṣálẹ̀,ju kí eniyan máa bá oníjà ati oníkanra obinrin gbé lọ.

20. Ní ilé ọlọ́gbọ́n ni à á tí ń bá nǹkan olówó iyebíye,ṣugbọn òmùgọ̀ a máa ba tirẹ̀ jẹ́.

21. Ẹni tí ń lépa òdodo ati àánúyóo rí ìyè, òdodo, ati iyì.

22. Ọlọ́gbọ́n a máa gba ìlú àwọn alágbáraa sì wó ibi ààbò tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé lulẹ̀.

23. Ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́pa ara rẹ̀ mọ́ kúrò ninu ìyọnu.

24. “Oníyẹ̀yẹ́” ni orúkọ ẹni tí ń gbéraga,tí ó sì ń ṣe mo tó báyìí-dà báyìí.

25. Ìrònú ohun tí ọ̀lẹ fẹ́ ni yóo pa á,nítorí ọwọ́ rẹ̀ kọ̀ láti ṣiṣẹ́.

26. Eniyan burúkú a máa ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ìgbà,ṣugbọn olódodo ń fúnni láìdáwọ́dúró.

27. Ohun ìríra ni ẹbọ eniyan burúkú,pàápàá tí ó bá mú un wá pẹlu èrò ibi.

28. Ọ̀rọ̀ ẹlẹ́rìí èké yóo di asán,ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹni tí ó fetí sílẹ̀ ni a óo gbàgbọ́.

-5-

29. Eniyan burúkú a máa lo ògbójú,ṣugbọn olóòótọ́ máa ń yẹ ọ̀nà ara rẹ̀ wò.

30. Kò sí ọgbọ́n, tabi òye, tabi ìmọ̀,tí ó lè dojú kọ OLUWA kí ó mókè.

31. Eniyan a máa tọ́jú ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun,ṣugbọn OLUWA ló ni ìṣẹ́gun.