Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 2:2-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Ẹ bá ìyáa yín wí, ẹ bá a wí,nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi,Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀.Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀àti àìsòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.

3. Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòòhòÈmi yóò sì gbé e kalẹ̀ lá ìwọṣọ gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a bí i.Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀,Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀Èmi yóò sì fi òùngbẹ gbẹ ẹ́.

4. Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́

5. Ìyá wọn jẹ́ aláìsòótọ́ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú.Ó wí pé, ‘èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi,tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi,aṣọ oríṣìíríṣìí, òróró àti ohun mímu’ lẹ́yìn.

6. Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nàÈmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.

7. Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn;Yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn.Nígbà náà ni yóò sọ pé,‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsìnyí lọ.’

8. Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi niàti ẹni tó fún un ní ọkà,ọtí-wáìnì tuntun àti òróróẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọpọ̀ Èyí tí wọ́n lò fún Báálì

9. “Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n,èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀.Èmi yóò sì gba ìrun àgùntàn irun àgùtàn àti ọ̀gbọ̀ mi padàmo ti fifun un láti bo ìhòòho rẹ̀.

10. Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hànlójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi

11. Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin:àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀,ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àṣàyàn ọdún rẹ̀.

12. Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run,Èyí tí ó pè ní èrèe rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn Olólùfẹ́ rẹ̀,Èmi yóò sọ wọ́n di igbó,àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.

13. Èmi yóò jẹ́ ẹ́ níyà fún gbogbo ọjọ́tó fi jo tùràrí sí Báálìtí ó fi òrùka àti ohun ọ̀ṣọ́ wọ ara rẹ̀ tán,tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ.Ṣùgbọ́n ó gbàgbé èmi,”ni Olúwa wí.

14. “Nítorí náà, èmi yóò tàn ánÈmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀

Ka pipe ipin Hósíà 2