Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jer 20:4-10 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Nitori bayi li Oluwa wi, sa wò o, emi o fi ọ le idãmu lọwọ, pẹlu gbogbo awọn ọrẹ rẹ, nwọn o ṣubu nipa idà awọn ọta wọn, oju rẹ yio si ri i, emi o si fi gbogbo Juda le ọwọ ọba Babeli, on o si mu wọn lọ ni igbèkun si Babeli, yio si fi idà pa wọn.

5. Pẹlupẹlu emi o fi ọrọ̀ ilu yi, pẹlu ẽre rẹ̀ ati ohun iyebiye rẹ̀, ati gbogbo iṣura awọn ọba Juda li emi o fi le ọwọ awọn ọta wọn, ti yio jẹ wọn ti yio si mu wọn lọ si Babeli.

6. Ati iwọ, Paṣuri, ati gbogbo awọn ti o ngbe inu ile rẹ ni yio lọ si igbekun, iwọ o wá si Babeli, ati nibẹ ni iwọ o kú si, a o si sin ọ sibẹ, iwọ ati gbogbo ọrẹ rẹ ti iwọ ti sọ asọtẹlẹ eke fun.

7. Oluwa, iwọ ti fi ọ̀rọ rọ̀ mi, emi si gba rirọ̀! iwọ li agbara jù mi lọ, o si bori mi; emi di ẹni iyọ-ṣuti-si lojojumọ, gbogbo wọn ni ngàn mi!

8. Nitori lati igba ti mo ti sọ̀rọ, emi kigbe, mo ke, Iwa-agbara, ati iparun, nitori a sọ ọ̀rọ Oluwa di ohun ẹ̀gan ati itiju fun mi lojojumọ.

9. Nitorina mo si wipe, emi kì yio mu ni ranti rẹ̀, emi kì yio si sọ ọ̀rọ li orukọ rẹ̀ mọ́. Ṣugbọn ọ̀rọ rẹ̀ mbẹ bi iná ti njó ninu mi ti a se mọ inu egungun mi, o si rẹ̀ mi lati pa a mọra, emi kò le ṣe e.

10. Nitoriti mo gbọ́ ẹgan ọ̀pọlọpọ, idãmu niha gbogbo, nwọn wipe: fi sùn, awa o si fi sùn. Gbogbo awọn ọrẹ mi, ati gbogbo awọn ẹgbẹ mi wipe: bọya a o tãn jẹ, awa o si ṣẹgun rẹ̀, a o si gbẹsan wa lara rẹ̀.

Ka pipe ipin Jer 20