Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 12:2-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Lákókò ìkórè, ọkùnrin náà rán ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí àwọn tí ń tọ́jú oko tí ó fi sílẹ̀, láti gba ìpín tirẹ̀ wá nínú ohun ọ̀gbìn oko náà.

3. Ṣùgbọ́n àwọn àgbẹ̀ wọnnnì lu ìránṣẹ́ ọkùnrin náà, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.

4. Ó sì tún rán ọmọ-ọ̀dọ̀ mìíràn sí wọn. Bí àwọn àgbẹ̀ tí tún rí ọmọ-ọ̀dọ̀ tí ó rán sí wọn; wọ́n lù ú. Àní, wọ́n tilẹ̀ dá ọgbẹ́ sí i lórí, wọn rán an lọ ni ìtìjú.

5. Ó sì tún rán òmíràn, èyí n nì wọ́n sì pa, àti ọ̀pọ̀ mìíràn, wọ́n lu òmíràn wọ́n sì pa òmiran.

6. “Ìránṣẹ́ kan ṣoṣo ló kù tí Baba olóko kò ì tí ì rán níṣẹ́, èyí ni ọmọ òun tìkárarẹ̀. Níkẹyìn ó ran an sí àwọn àgbẹ̀ náà, pẹ̀lú èrò pé, ‘Wọn yóò bu ọlá fún ọmọ òun.’

7. “Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ọmọ baba olóko, wọ́n sọ fún ara wọn pé, ‘Ọmọ rẹ̀ ló ń bọ̀ yìí. Òun ni yóò jogún oko yìí tí baba rẹ̀ bá kú. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, lẹ́yìn náà oko náà yóò di tiwa.’

8. Báyìí ni wọ́n mú ọmọ náà tí wọ́n pa á. Wọ́n gbé òkú rẹ̀ kúrò nínú oko.

9. “Kí ni ẹ rò pé baba olóko yóò ṣe nígbà tí ó bá gbọ́ ohun tí ó ṣélẹ́. Dájúdájú yóò pa àwọn ẹni ibi wọ̀nyí. Yóò sì gba àwọn olùtọ́jú mìíràn sínú oko rẹ̀.

10. Tàbí ẹ̀yin kò ì tí ka ẹṣẹ yìí nínú ìwé mímọ́:“ ‘Òkúta tí àwọn ọmọ̀lé ti kọ̀ sílẹ̀òun náà ni ó di pàtàkì igun ilé.

Ka pipe ipin Máàkù 12