Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sekaráyà 10:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ bèèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná,tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn,fún olúkúlúkù koríko ní pápá.

2. Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán,àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké,wọn sì tí rọ àlá èké;wọ́n ń tu ni nínú láṣán,nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn,a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́àgùntàn kò sí.

3. “Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran,èmi o sì jẹ àwọn olórí níyànítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀,ilé Júdà wò,yóò ṣi fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.

4. Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá,láti ọ̀dọ̀ rẹ ni igi-èèkàn àgọ́ tí wá,láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá,láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.

5. Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrinalágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun,nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn,wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.”

6. “Èmi o sì mú ilé Júdà ní agbára,èmi o sì gba ilé Jósẹ́fù là,èmi ó sì tún mú wọn padànítorí mo tí ṣàánú fún wọn,ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tìí ta wọ́n nù;nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn,èmi o sì gbọ́ ti wọn

Ka pipe ipin Sekaráyà 10