Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Náhúmù 3:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ègbé ni fún ìlú ẹ̀jẹ̀ nì,gbogbo rẹ̀ kún fún èké,àti olè,ìja kò kúrò!

2. Ariwo pàṣán àti ariwokíkùn kẹ̀kẹ́ ogunàti jíjó ẹṣin àti gbígbọ̀nkẹ̀kẹ́ ogun jìgìjìgì!

3. Ológun orí ẹṣin ń fi ìgbónáraju ìdà wọn mọ̀nàmọ̀nàọ̀kọ̀ rẹ̀ ti ń dán yanran sí òkè!Ọ̀pọ̀lọpọ̀ si ní àwọn ẹni tí a pa,àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú;òkú kò si ni òpin;àwọn ènìyàn sì ń kọsẹ̀ lára àwọn òkú.

4. Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn panṣágààgbèrè tí ó rójú rere gbà,Iyá àjẹ́ tí ó sọ́ àwọn orilẹ̀-èdè di ẹrúnipa àgbèrè rẹ̀àti àwọn ìdílé nipa ìṣe àjẹ́ rẹ̀.

5. “Èmi dojú kọ ọ́,” ni Olúwa awọn ọmọ ogun wí.“Èmi ó si ká aṣọ ìtẹ́lẹ̀dì rẹ ní ojú rẹ,Èmi yóò sì fi ìhòòhò rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdèàti ìtìjú rẹ̀ han àwọn ilẹ̀ ọba.

6. Èmi yóò da ẹ̀gbin tí ó ni ìríra sí ọ ní ara,èmi yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà.

7. Kò sí ṣe pé, gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé,‘Nínéfè ṣòfò: Ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”

8. Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tébésì lọ,èyí tí ó wà ní ibi odò, Náílìtí omi sì yí káàkiri?Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀,omi si jẹ́ odi rẹ̀.

9. Etiópíà àti Éjíbítì ni agbára rẹ, kò sí ní òpin;Pútì àti Líbíà ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.

10. Ṣíbẹ̀ ṣíbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùno sì lọ sí oko ẹrú.Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀ní orí ìta gbogbo ìgboro.Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin,gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè

11. Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara;a ó si fi ọ́ pamọ́ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.

Ka pipe ipin Náhúmù 3