Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 14:19-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. “Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-àrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunu mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,

20. bo tilẹ̀ jẹ́ pé Nóà, Dáníẹ́lì àti Jóòbù wà nínú rẹ, bí mo ti wà láàyè ni Olúwa Ọlọ́run wí wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbà là.

21. “Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí: Báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jérúsálẹ́mù-èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-àrùn-láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!

22. Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀-àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ ó rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ ó rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jérúsálẹ́mù—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.

23. Nígbà tí ẹ bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ ó mọ̀ pé n kò ṣe nǹkan kan láì nídìí, ni Olúwa Ọlọ́run wí.”

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 14