Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 1:7-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Síbẹ̀, èmi yóò ṣàáànú fún ilé Júdà, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”

8. Lẹ́yìn ìgbà tí ó (gba ọmú lẹ́nu rẹ̀) Lo-rúhámà, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni

9. Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ámì, (kì í ṣe ènìyàn mi) nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.

10. “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yóò pọ̀ bíi iyanrìn etí òkun tí a kò le wọ̀n, tí a kò sì le è kà, yóò síṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘ọmọ Ọlọ́run alààyè.’

Ka pipe ipin Hósíà 1