Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 4:34-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. Ní òpin ìgbà náà, Èmi, Nebukadinéṣárì gbé ojú ù mi sókè sí ọ̀run, iyè mi sì sọjí. Mo fi ọpẹ́ fún Ọ̀ga Ògo; mo fi ọlá àti ògo fún ẹni tí ó wà láéláé.Ìjọba rẹ̀ ìjọba títí ayé niìjọba rẹ̀ wà láti ìran dé ìran

35. Gbogbo àwọn ènìyàn ayéni a kà sí asán.Ó ń ṣe bí ó ti wù ú,pẹ̀lú àwọn ogun ọ̀run,àti gbogbo àwọn ènìyàn ayétí kò sì sí ẹnì kankan tí ó lè dí i lọ́wọ́tàbí sọ fún un wí pé: “Kí ni ìwọ ń ṣe?”

36. Ní àkókò kan náà, iyè mi padà, ọlá àti ògo dídán mi padà tọ̀ mí wá fún ògo ìjọba mi. Àwọn ìgbìmọ̀ àti àwọn ọlọ́lá mi, wá mi rí, wọ́n sì dá mi padà sórí ìjọba mi, mo sì di alágbára ju ti ìṣáájú lọ.

37. Báyìí, èmi, Nebukadinéṣárì fi ọpẹ́, mo sì gbé Ọlọ́run ga, mo sì fi ògo fún ọba ọ̀run, nítorí pé gbogbo nǹkan tí ó ṣe ló dára, gbogbo ọ̀nà rẹ̀ sì tọ́. Gbogbo àwọn tó sì ń rìn ní ìgbéraga ni ó le rẹ̀ sílẹ̀.

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 4